Ondo 2020 Tribunal: Ìgbìmọ̀ olùgbẹ̀jọ́ ìbò gómìnà yóò gbérasọ lọ́jọ́ Iṣẹgun

Igbimọ igbẹjọ idibo Gomina ipinlẹ Ondo ti n palẹmọ lati bẹrẹ ijoko.
Ninu idibo naa to waye ni ọjọ Kẹwaa, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020 ti Gomina Rotimi Akeredolu ti ẹgbẹ oṣelu APC lo gbegba oroke.
Adajọ Umar Abubakar ni yoo lewaju awọn adajọ meji mii ti yoo gbẹjọ ọhun bẹrẹ lati ọjọ Kẹjọ oṣu Kejila ọdun 2020.
Agboola Ajayi: Igbákejì gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo tó fẹ́ yẹ àga mọ́ Akeredolu nìdí
Agbẹjọro oludijẹ ẹgbẹ PDP, Eyitayo Jegede tii ṣe Onyechi Ikpeazu lo fiwe pe Gomina Akeredolu ati ẹgbẹ APC fun aṣemaṣe to tako ofin ilẹ yi.
Lara kudiẹkudiẹ to mẹnu ba ni pe Gomina Akeredolu kọ ni ẹgbẹ rẹ dibo yan lati ṣoju wọn ninu idibo Gomina.
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa akínkanjú obìnrin alága àjọ elétò ìdìbò Ghana 2020
- Wo ibi mẹ́rìnlá tí o kò gbọdọ̀ gbé ọkọ̀ rẹ sí lásìkò yìí...
- Ọdun 2012, 2016 àti 2020 ni John Mahama àti Nana Akufo-Addo ti jọ ń figagbága dupò aàrẹ Ghana
- Ó tó gẹ́! Agbẹjọ́rò Maina yọ ọwọ́ kúrò nínú ìgbẹ́jọ́, Ó lóun kò ṣé mọ̀
Ni ibamu pẹlu ohun tofin ilẹ yi sọ, o ni Gomina ipinlẹ ko le jẹ alaga ẹgbẹ ti yoo yan ẹlomii lati dije dupo.
O salaye pe Gomina ipinlẹ Yobe, Mai Mala Buni lẹni to tako ofin yi nipa pe o di ipo alaga ẹgbẹ APC mu to si tun yan Akeredolu lati dije dupo Gomina.
Yatọ si alaye yi gẹgẹ bi kan lara idi ti ko yẹ ki wọn fi gba iyansipo Akeredolu wọle, Jegede tun ni iwa janduku waye lawọn ijọba ibilẹ kan ati aaye idibo lawọn ibomiran.
























