Oluwo: Ìgbà mẹ́rin rèé tí ọ̀rọ̀ Oluwo ti Iwo dá awuyewuye sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, Instagram/emperortelu1
Ninu ọba alade ilẹ Kaarọ ojiire, o fẹẹ ma si eleyi ti o sunmọ ọba ilu Iwo Abdulrasheed Adewale nibi ka jẹ olokiki.
Laye ode oni ti ti ọlaju oju opo ayelujara ti gbilẹ, iroyin orisirisi nipa Ọba yii lawọn eeyan ma n gbe kaakiri.
Pupọ ninu awọn iroyin wọnyi a maa ti ati ọwọ ọba Abdulrasheed wa nitori pe oun gaan ma n fi ọrọ si oju opo Instagram nipa ohun to ba n ṣẹlẹ ni ayika rẹ.
- Ṣeyi Makinde ṣé ìfilọ́lẹ̀ àwọn olùdarí ìbùdókọ́, ó yan Auxilliary lálaga ìgbìmọ̀
- Aláàfin ìlú Oyo, Ikú Bàbá Yèyé tún bímọ tuntun làǹtì lanti
- Gbogbo ẹ̀yin ọ̀ba abẹ́ mi, tí ẹ̀ ń ta ilẹ̀ ìlú, ẹ kò ní fara re lọ - Oluwo
- Ìtọ̀ ló ní òun fẹ́ tọ̀ tó fi bọ́ sílẹ̀ nínú ọkọ̀, àfi bó ṣe bẹ́ sódò
- Ìjàmbá ọkọ̀: Èèyàn méje dèrò ọ̀run, àwọn ọ̀dọ́ sun ọkọ̀ Dangote
- Bí orí ṣe yọ akẹ́kọ̀ọ́ Cameroon kan tó bọ́ lọ́wọ́ Coronavirus rèé
- 'Mo lè jẹ eku mẹ́wàá lọ́jọ́ kan'
Ẹ jẹ ki a a ran ara wa leti diẹ ninu awọn iroyin to jẹyọ latara ọrọ ti ọba alade yi sti ọ ati awọnnkan to ṣe to mi igboro titi
#Oluwo Divorce
Kabiesi ni idi ti oun fi kọ olori Chanel silẹ ni pe iyatọ n waye laarin awọn ti ko ṣee yanju.
Iroyin yii mi igboro titi ti awọn eeyan si bẹrẹ si ni sọ pe ko yẹ ki ọba Alade kọ iyawo rẹ silẹ.
Oluwo ko sọ ni pato ohun to fa ikọsilẹ naa lasiko yii ju pe ki awọn eeyan dẹkun bibu ọla fun Channel gẹgẹ bii iyawo oun mọ.

Oríṣun àwòrán, @others
Ọmọ kan ni Chanel bí fún Oluwo, orukọ rẹ a si maa jẹ Oduduwa.
Olori Chanel Chin jẹ ọmọ orilẹ-ede Jamaica, baba rẹ si ni olorin takasufe ti ọpọ eeyan mọ si "Bobo Zaro."
- Ìdí tí LASEMA fi dáwọ́ wíwá ọkùnrin tó bẹ́ s'ódò 3rd Mainland Bridge dúró
- Mercy Aigbe: Àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kẹ̀yìn sí í pé ó ní káwọn ọmọge gbọ́n àpò baálé ilé tí wọ́n ń fẹ́ gbẹ
- Buhari, kọjú mọ́ ìṣèjọba rẹ ni, má dùnkokò mọ́ alátakò àti oníròyìn - PDP
- Torí ǹkan oṣù, Iléèwé pàṣẹ kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tú síhòhò
'Èmi ni atọ́nà oyè Wàzírì nílẹ̀ Yorùbá'
Ọrọ o ṣe oye Waziri ilẹ Yoruba ko ṣe oye Waziri jẹ ọkan ti o da awuyewuye silẹ nigba ti Oluwo ilu Iwo sọ ọ.

Ki lo ṣẹlẹ gaan? Oluwo kede pe oun fẹ danikan ṣe ifilọlẹ ẹni ti yoo jẹ Waziri fun gbogbo ilẹ Yoruba lalai fi ti awọn ọba toku tabi awọn onimọ Islam miran ṣe.
Ọrọ ko dun mọ awọn Alfa ilẹ Yoruba ninu ti o si di fa kin fa a laarin wọn ati Oluwo.
Lẹyin o rẹyin, Oluwo fi ẹni to wu u jẹ oye yi ti awọn Alfa si ni igbesẹ rẹ ko tọna nitori awọn onimọ́ ẹsin lo yẹ kio yan Waziri kii ṣe ọba.
Mo ti ṣetán láti daríi ìfẹ̀họ́nú hàn lòdì sí ìpànìyàn - Olúwó
Oluwo ti ilu Iwo, Ọba Abdulrasheed Adewale Akanbi, sọ pe oun ti ṣe tan lati daríi ifẹhonuhan lodi si ipaniyan ati iwa ibajẹ ti o gbode kan lorilẹ-ede Naijiria.
O bu ẹnu atẹ lu iha ti ijọba kọ si ọrọ ipaniyan ṣowo, ati pe pipaniyan fun ṣiṣe oogun owo buru ju iwa ijinigbe lọ.

Oríṣun àwòrán, @BolanleCole
Oluwo tẹsiwaju pe, eto aabo ara ilu jẹ ojuṣe akọkọ fun ijọba.
O si bu ẹnu atẹ lu iwa ifẹmiṣofo ti o ti di tọrọ-kọbọ lorilẹ-ede yii.
Ẹ má gbé ẹ̀kú eégún 1960, tó ń rùn wọ ààfin mi
Lasiko ajọyọ ọdun Egungun to waye nilu Iwo ni Oluwo ti sọ ọrọ.
Ninu ifọrọwanilẹwo pẹlu BBC Yoruba, Oluwo ni ọna ati gbe aṣa larugẹ ni ọdun egungun yii jẹ amọ oun ko ni gba ki egungun kankan rinrin idọti wọ aafin oun.

"Kosi eegun kan ti yoo wọ aafin mi to gbọdọ dọti. Kii ṣe wipe wọn yoo gbe ẹku 1960 wa, to ti dọti, to n run. Mo fẹ ki egungun to ba wa, jẹ nnkan iwuri fun awọn ọmọde ati awọn agba, ki gbogbo eeyan lee fi ọwọ kan awọn eegun yii."Kabiyesi tẹsiwaju wi pe, ọdun egungun kii ṣe fun ibọriṣa, bikoṣe fun igbelaruge aṣa ati ere idaraya.












