Oluwo: Àwọn Alfa ń ‘copy’ mi ni wọ́n ṣe yan Waziri míràn

Oluwo ti ilu Iwo, Ọba Abdulrasheed Akanbi ti bu ẹnu atẹ lu bi ajọ àwọn ìmáàmù ati Alfa se kéde Ustaz Abdul- Lateef Adekilekun gẹ́gẹ́ bí Waziri tuntun fún ilẹ̀ Yoruba.
Lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ lori oye tuntun naa, Ọba Akanbi ni oun nikan loun lasẹ lati fi Waziri jẹ, nitori ọba lo ma n fi Waziri jẹ, kii se oye ti awọn ajọ̀ musulumi tabi alfa lee fi jẹ.
Oluwo ti Ilu Iwo ni, o gbọdọ ye awọn ọmọ ilẹ Yoruba pe oye ọba ni oye naa, nitori naa ni oun se yan Waziri Yaquob Abdul-Baki Mohammed, lati ọdun 2017.
- Ajé ò! Ẹ wo fídíò òfò àti àdánù tó wáyé níbi ìkọlù sáwọn àjèjì ní South Africa
- Òògùn olóró tí àwọn ọmọ Naijiria ń tà ló fa ìkọlù - South Africa
- Ṣé Zimbabwe dùn gbé bí lásìkò yìí ju àkókò ìṣèjọ̀ba Mugabe lọ?
- "Mugabe fi ìgboyà dáábò bo ilẹ̀ Áfíríkà lọ́wọ́ ìmúnisìn"
- Àwọn ọ̀rọ̀ apanílẹ̀rín tí Mugabe sọ tó jẹ́ mánigbàgbé
O fikun wi pe, gbogbo ibi ti wọn ti n yan Waziri, ọba lo n yan. O ni awọn imaamu yan Waziri Mumini ni, eyi to yato si ti oun.

Oríṣun àwòrán, Instagram/Oluwo of Iwoland
Oluwo ni gẹgẹ bi ọba to ba lori oun gbogbo, ti kosi jẹ baalẹ ri, ni oun se gbagbọ wi pe ẹtanu ni awọn alfa fi yan Waziri ti won.
Ti a ko ba gbagbe, ajọ awọn imamu ti kede wi pe Ustaz Abdul- Lateef Adekilekun gẹgẹ bi Waziri tuntun ti ilẹ Yoruba.
Àwọn ìmámù ilẹ̀ Yoruba kọ ọ̀rọ̀ sí Oluwo lẹ́nu, wọ́n yan Waziri tuntun
Saaju ni ajọ imaamu ni ilẹ Yoruba ti tako Oluwo ti Iwo, Oba Abdulrasheed Akanbi lori yiyan ẹni ti yoo jẹ oye Waziri ti ilẹ Yoruba, ti wọn si yan Ustaz Abdul- Lateef Adekilekun gẹgẹ bi Waziri tuntun.
Aarẹ Ajọ imaamu ati awọn Alfa ni iwo-oorun orilẹede Naijiria, Edo ati ipinlẹ Delta, Sheikh Jamiu Bello lo ni ko tosi Ọba Akanbi lati gbe oye naa lo si ilu rẹ Iwo.

Oríṣun àwòrán, Instagram/Oluwo_of_Iwoland
Sheikh Bello ni ẹni tuntun ti wọn yan naa jẹ akẹẹkọ gboye ninu ẹsin musulumi, ti o si tun jẹ akowe, onitan ati ẹni ti n saanu.
Ti a ko ba gbagbe, ọdun 2018 ni Oluwo bura pe oun yoo yan Yaquob Abdul-Baki Mohammed gẹgẹ bi Waziri ti ilẹ Yoruba.












