APC Kogi Primaries: Yahaya Bello la àwọn olùdíje mẹ́sàn án mọ́lẹ̀ fún àṣíá gómìnà ìpínlẹ̀ Kogi

Oríṣun àwòrán, others
Gomina Yahaya Bello lawọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC ni ipinlẹ Kogi tun gbe aṣia ẹgbẹ oṣelu naa le lọwọ.
Oun ni wọn fun lati fi dije ipo gomina lasiko idibo ti yoo waye loṣu kọkanla ọdun yii.
Ibo ẹgbẹrun mẹta ati ọdunrin o le mọkandinlaadọrin ni Yahaya fi bori awọn oludije mẹsan miran ti wọn jọ sa ere ije naa eyi to waye nilu Lọkọja.

Oríṣun àwòrán, @others
Gẹgẹ bii gomina Abubakar Badaru ti ipinlẹ Jigawa to ṣe alaga eto idibo naa ṣe sọ, Ọgbẹni Babatunde Irukera lo gbe ipo keji pẹlu ibo mọkandinlaadọfa ti Hassan Bewa si ṣe ipo kẹta pẹlu ibo mẹrinlelogoji.
Ibo mẹwaa pere ni Yahaya Audu ni ti Sanni Abdullahi ni tirẹ si ni meje.

Oríṣun àwòrán, @others
Ọjọ kẹrindinlogun, oṣu kọkanla, ọdun 2019 ni eto idibo si ipo gomina ni ipinlẹ Kogi yoo waye.








