Ọba Atah ti Ayede Ekiti, Ọba Adeleye Orisagbemi dèrò ilé ìwòsàn l'Ekiti lẹ́yìn tí àwọn agbébọn rọ́jò ìbọn fún un

Ọba Adeleye Orisagbemi

Oríṣun àwòrán, Ogunmoko

Ọba alade kan ni ipinlẹ Ekiti, Atah ti Ayede Ekiti, Ọba Adeleye Orisagbemi ti dero ile iwosan lẹyin ti awọn agbebọn kan yinbọn lu.

Ẹni ti iṣẹlẹ naa ṣoju rẹ sọ pe iṣẹlẹ ọhun waye lọjọ Aiku laarin ilu Isan si Ayede Ekiti ni nnkan bi aago mẹsan alẹ lasiko ti ori ade naa n bọ lati ipada kan.

Awọn oṣoju mi koro sọ pe awọn agbebọn naa gbiyaju lati ji kabiesi naa gbe, amọ wọ dana ibọn fun lẹyin ti igbiyanju wọn fori ṣopọn.

Nibo ni ọ̀rọ̀ de duro bayii?

Ọba naa ti n gba itọju nile iwosan bayii kan lasiko ti an ko iroyin yii jọ.

Gbogbo akitiyan lati kan si ori ade naa lo ja si pabop, amọ agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa Ekiti, Sunday Abutu fidi iroyin naa mulẹ fun BBC Yoruba.

Àkọlé fídíò, Gani Adams: Ẹniyan ma n ra aye gbe ni

Amọ Abutu sọ pe ilu Ijero Ekiti ni Ọba Orisagbemi ti n bọ, tako iroyin to kọkọ sọ pe ilu Isan lo ti n bọ ko to kagbako awọn ẹni ibi naa.

O ni awọn ti bẹrẹ iṣẹ lati ṣawari awọn agbegbọn ọhun, ati pe Oba Orisagbemi ti n gba itọju lọwọ lẹyin ti awọn gbe lọ sile iwosan.

Àkọlé fídíò, Khadijat Okunnu:Olùdíje ipò ààrẹ Nàìjíríà tó sọ pé nkán gbódọ̀ dàrú ní Nàìjíríà kò

Ikọlu awọn agbebọn si awọn Ọba ilẹ Yoruba

Ti ẹ ko ba gbagbe, inu oṣu kọkanlan ọdun 2020 ni awọn agbebọn kan ṣekupa Ọba Israele Adewusi, to jẹ Olufon ti ilu Ifon, ni ipinlẹ Ondo.

Àkọlé fídíò, Money Ritual: Ǹ kò le bèèrè

Nigba to di inu oṣu Kẹfa ọdun 2021, awọn agbebọn ji Eleda ti Eda-Ile Ekiti gbe, iyẹn Ọba Benjami Osho.

Iṣẹlẹ ijinigbe Eleda yii lo waye ni nnkan bi oṣu meji ti awọn agbebọn kan ti kọkọ ji Ọba David Adegboyega, to jẹ Obadu ti Ilemosho gbe, ko to gba itusilẹ lẹyin ọjọ marun un.

Àkọlé fídíò, Ifọrọwanilẹnuwo pẹlu Mc Lively aderinposonu Naijiria