NSCDC mú ọkùnrin tó ń bá ọmọ ọdún mẹ́sàn án tó jẹ aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀ ni Kwara

NSCDC

Oríṣun àwòrán, @NSCDC

Ọwọ́ tẹ bàbá ẹni ọdun 60 níbi tó ti n bá ọmọ ọdún mẹ́sàn-án lòpọ̀.

Ajọ ẹṣọ alaabo abo ara ẹni, laabo ilu, Civil Defence nipinlẹ Kwara , ti mu ọkunrin ẹni ọgọta ọdun kan to fi ipa ba ọmọ ọdún mẹsan lo pọ.

Iroyin sọ pe Jerimiah Oyedoki fi ipa ba ọmọdebinri naa to jẹ ọmọ alajọgbele rẹ ni ilu Kaiama nijọba ibilẹ Kaiama nipinlẹ naa.

Ileesẹ iroyin ori ayelujara, The Guide sọ pe nibi ti Oyedoki ti n ba ọmọ naa lo pọ̀ ni ọwọ awọn òbí ọmọ naa ti tẹ.

Eyi to mu ki wọn o pariwo, ti wọn si fi ọrọ to ajọ NSCDC leti.

Àkọlé fídíò, Teachers retirement age and years of service: Ìrírí àwọn àgbà olùkọ́ ṣì wúlò fún àwa ọ̀dọ́

Agbenusọ ajọ naa nipinlẹ Kwara, Babawale Afolabi sọ fun awọn akọroyin pe ni nkan bi aago márùn-ún àbọ̀ irọlẹ ni Jerimiah Oyedokun to n gbe ni agboole Ileloja, Kaiama fi ipa ba ọmọ naa lo pọ.

Àkọlé fídíò, Tunde Bakare: Àjọjẹ kò dún bẹ́nìkan kò ní ló fa ìjà S Igboho,bẹ́ẹ̀ ìjọbati gbẹ́rù kọjá orí

O ni aadọta Naira ni afurasi naa sọ pe oun fi tan ọmọbìnrin naa.

Wọn ti gbe ọmọ naa lọ si ileewosan ijọba ni Kaiama fun awọn ayẹwo to peye.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

Bakan naa ni Ọgbẹni Afolabi sọ pe ẹjọ ọkùnrin naa ti wa ni olu ileesẹ ajọ NSCDC, ti wọn o si gbe e lọ sile ẹjọ laipẹ.