Aisha Buhari: Aya Ààrẹ Buhari ké sí àwọn aya gómìnà pé kí wọ́n lọ paná ìdàrúdàpọ̀ ágbègbè kóówá

Oríṣun àwòrán, @Aishat
Aisha Buhari rọ àwọn aya gómìnà láti gbárùkù ti ètò àláafíà láwùjọ wọń.
Iyawo Aarẹ, Hajia Aisha Buhari, ti rọ awọn aya gomina ni Naijiria lati ṣe koriya fawọn obinrin, ki wọn si fọwọsowọpọ pẹlu awọon ọdọ atawọn obinrin ẹgbẹ wọn ki alaafia le jọba ni Naijiria.
Aisha lo sọ ọrọ naa nibi idanilẹkọ kan lori ọna ti alaafia le gba jọba lawujọ pẹlu ifọwọsowọpọ awọn ọdọ atawọn obinrin lẹyin ajakalẹ arun Covid-19.
Aya Aarẹ, ti olubadamọran agba fun Aarẹ lori ọrọ awọn obinrin, Hajo Sani, ṣoju fun sọ pe, Covid-19 ti da rogbodiyan silẹ kaakiri agbaye eyi to n ṣokunfa oriṣiriṣi ifẹhonuhan ati iwa ipa lawujọ, paapa si awọn obinrin.
- Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀
- Ṣé ẹ rántí àkọ́lé àwọn ìwé àkàgbádùn yìí?
- Wo àwọn oúnjẹ márùn ún tó ń mú kí àtọ̀ ọkùnrin dára síi
- Irọ́ ni pé mò kò "Palliatives" pamọ́ sí ilé mí-Abike Dabiri-Erewa
- Ọdun 2012, 2016 àti 2020 ni John Mahama àti Nana Akufo-Addo ti jọ ń figagbága dupò aàrẹ Ghana
Aisha Buhari ni awọn ọmọde atawọn obinrin ni atubọtan arun naa yoo pa lara ju nitori aini anfani si eto ẹkọ to yanranti ati eto ilera to peye.
Ninu atẹjade kan lati ọọfisi iyawo Aarẹ, o ni "ojuṣe wa ni gẹgẹ bi ẹni to wa lori ipo adari lati gbaruku ti awọn obinrin ati awọn ọdọ fun igbedide alaafia lawujọ."
Minisita fun ọrọ awọn obinrin, Dame Pauline Tallen, ti amugbalẹgbẹ rẹ, ọmọba Dame Pauline Tallen ṣoju fun sọ pe kii ṣe akoko yii lo yẹ ki awọn dakẹ nitori awọn ohun to n ṣẹlẹ kaakiri agbaye.
O ni ileeṣẹ to n ri si ọrọ awọn obinrin labẹ oun yoo ṣe gbogbo ohun to yẹ lati ri pe alaafia wa lawujọ, o si jẹ eyii to ṣe é gbe fun gbogbo eeyan.
Tallen rọ gbogbo ọmọ Naijiria gẹgẹ bi ẹnikankan lati mu ọrọ ẹkọ awọn ọmọ obinrin ni ọkunkundun.
- Ọdun 2012, 2016 àti 2020 ni John Mahama àti Nana Akufo-Addo ti jọ ń figagbága dupò aàrẹ Ghana
- Gbọ́yì-sọ̀yí àti ìròyìn èké láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ wa ló ṣáábà ma ń da ìgbéyàwó àwọn òṣèré rú- Ọpẹ Ayeola
- Ọlọ́jọ́ padà dé! Arákùnrin tó 'jíǹde' ní mọ́ṣúárì tí kú
- Amẹrika ti yọ àfikún owó Físà kúrò fún arìnrìnàjò Nàìjíríà
Iyawo gomina ipinlẹ Ekiti, to tun jẹ alejo pataki nibi idanilẹkọ naa, Erelu Bisi Fayemi mẹnuba ojuṣe awọn aya gomina nipa idagbasoke awujọ.
Lara awọn eeyan Pataki to wa nibi idanilẹkọ naa ni aṣoju ilẹ Gẹẹsi si Naijiria nipa eto ọrọ aje, Helen Grant, ati alaga ẹgbẹ awọn ọmọ Naijiria nilẹ okere, Abike Dabiri-Erewa.
- Góòlù pọ̀ ní ìlú Madaka ṣùgbọ́n wọn kò ní ọ̀nà fún ọgọ́rùn ún ọdún
- Ta ni ìgbẹ́jọ́ ìbò gómìnà Ondo yóó gbè nínú Akeredolu àti Jegede?
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa akínkanjú obìnrin alága àjọ elétò ìdìbò Ghana 2020
- Buhari, pàṣẹ f'àwọn Gómìnà pé kí wọ́n jáwọ́ nínú èróǹgbà láti ná N17trillion owó ìfẹ̀yìntì òṣìṣẹ́













