Jemila dáná sún ilé ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ àti ọ̀rẹ́bìnrin tó bá nílé

Oríṣun àwòrán, Lagos Police Command
Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ìpińlẹ̀ Eko tí mú obìnrin ẹni ọdún mọ́kàndílógún kan tó dána sun ilé ọ̀rẹ́kùnrin tó n fẹ́ tẹ́lẹ̀ àti ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ tó bá nílé.
Ọmọbinrin náà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jemila Ibrahim àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Fatima Mohammed ẹni ọdún mọ́kànlélógún lágbègbè Monkey village, Festac nílù Eko.
Gẹ́gẹ́ bi ọ̀gá agbẹnusọ ọlọ́pàá ìpińlẹ̀ Eko Muyiwa Adejobi ṣe sọ, ìṣẹ̀lẹ̀ náà wáye ni ọjọ́rú, ọjọ́kejìdínlogún, oṣù kọkànlá ọdún yìí.
- Ìtumọ̀ àbàdòfin lórí omi tí ìjọba tẹramọ́ tó n bí àwọn ọmọ Nàìjíríà nínú rèé
- Ìjọba Naijiria faraya nínú lẹ́tà tó kọ sí CNN lórí ìwádìí rẹ̀ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Lekki Toll Gate
- Iṣu ata yáan yàan! Iṣẹ́ fẹ́ bọ́ lọ́wọ́ ọlọ́pàá tó gba N100k lọ́wọ́ awakọ̀ tó gba"One way" l'Eko
- Ẹ jọwọ, ẹ ba mi bẹ ìyàwó mi kí ìgbéyàwó mi ma baà túká - 9ice

Oríṣun àwòrán, Lagos Police Command
Ó sàlàyé pé ni kété ti Mohammed gbọ́ nípa ǹkan ti ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ nígbà kan ri Jemila fẹ́ ṣe ló sáre lọ si ilé rẹ̀, sùgban ẹ̀pa kò bóró mọ́ nígbà ti yóò fi débẹ̀, ilé rẹ̀ ti múná.
- Wo ohun mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ̀ tí o bá fẹ́ lọ fún ìsinmi lẹ́yìn Covid 19
- Kíni àjọ ọlọ́pàá ń ṣe lórí bí agbófinró ṣe ń ṣèèṣì pànìyan lójoojúmọ́?
- DSS ti fi ẹ̀sọ́ àbò abẹnugan ilé ìgbìmọ̀ asofin tó pa fẹ́ndọ̀ l'Abuja sátìmọ́lé
- Wọ́n ti rí òkú Alága ẹgbẹ́ APC ní Nasarawa tí àwọn agbébọn jí gbé lọ́jọ́ Satide
Mohammed gbìyànjú láti dóòlà, ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀, Rabi nínú iná náà tó sì gbe lọ si ilé ìwòsàn, nibi tó ti pada pàdánù ẹ̀mí rẹ̀ lọ́jọ́ sátide, ọjọ́kọkànlélógún, ọdún 2021.
Adejobi fi kún pé, kọ́mìsọ́nà ọlọ́pàá nípìnlẹ̀ Eko, Hakeem Odumosu ti páá lásẹ̀ pé ki wan gbé ẹja náà lọ sí Panti fún ìwádìí tó dájú














