Yemi Farounbi: Yorùbá yóò dáàbò bo ara rẹ́, bí ìjọ́ba bá kùnà láti ràgà bò wọ́n

Àkọlé fídíò, Yemi Farounbi: Yorùbá yóò dáàbò bo ara rẹ́, bí ìjọ́ba bá kùnà láti ràgà bò wọ́n

Aṣoju Naijiria tẹ́lẹ̀ lorileede Philipines, Ambassador Yemi Farounbi ti ni Sunday Igboho n ja fun ẹ̀tọ́ awọn eniyan rẹ ni lo se n jijagbara nitori naa ko ṣẹ si ofin.

Yemi Farounbi, lasiko to n ba BBC Yoruba sọ̀rọ̀ ni Igboho n tẹle ofin Naijiria to fun awọn eeyan laṣẹ lati da aabo bo ara wọn ni.

O fikun wi pe lati ọdun to ti pẹ ni Ilẹ Yoruba ti n pe fun atunto Naijiria, ki ẹya kọọkan ma a sakoso ara wọn, amọ awọn to n se ijọ́ba ko gba.

O tun woye pe ko si aar kankan tabi oloselu to le mu atunto ba Naijiria nitori ọ̀pọ̀ ohun to ti bajẹ́, awọ̀n igbesẹ́ to si gbọ̀dọ̀ gbe, bii lilọ̀ sile asofin ko le ran an lọ́wọ́.

Àwọn ìtàn mánigbàgbé tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Nibayii. o wa rọ awọn Yoruba lati fi imọ sọkan nitori ibaṣepọ to dan mọran ni o le e mu ọjọ ọla to dara ba awọn ọmọ Yoruba.