Ekiti Maternity Leave: Ìjọba Ekiti ní ìdẹ̀rùn àwọn aráàlú tó jẹ wọ́n lógún ló fa ìsinmi oṣù mẹ́fà fáwọn ìyálamọ

Oríṣun àwòrán, Silver Lining NG
Awọn obinrin to jẹ osisẹ ijọba nipinlẹ Ekiti ti bẹrẹ si n gboriyin fun ijọba ipinlẹ naa, lẹyin to kede isinmi oloṣu mẹfa fun awọn obinrin to jẹ oṣiṣẹ ijọba to ba ṣẹṣẹ bi ọmọ tuntun.
Lara awọn eeyan naa to ba BBC sọrọ sọ pe, inu wọn dun pupọ fun igbeṣẹ naa ti ijọba ọhun gbe.
Arabinrin Kemi sọ pe "Igbesẹ yii dara pupọ, o si jẹ eyi ti yoo fun awọn obinrin laaye lati ṣe itọju ọmọ tuntun ti wọn ṣẹṣẹ bi.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Sunday Igboho gba àwọn èèyàn Soka n‘Ibadan sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọmọ onílẹ̀ tó wá ṣọṣẹ́
- Àìsí ẹ̀rọ ìgbàlódé fún bàálù láti bà ní Nàíjíríà, mú káwọn bàálù láti òkè òkun lọ bà sí Ghana
- Ẹ san ₦200,000 fún Sowore lórí bí ẹ ṣe ń fi ẹjọ́ falẹ̀ - Iléẹjọ́ pàṣẹ fún ìjọba
- Buhari, èyí to fí ogún ọdún pilẹ̀ wèrè lórí ètò ààbò Nàìjíríà tó gẹ́ - Bishop Kukah
Kẹmi ni akoko isinmi naa yoo fun awọn abiyamọ laye lati ṣe itọju to peye fun ara wọn ati fun ikoko to ṣẹṣẹ wa saye.
O tẹ siwaju pe "Isinmi oṣu mẹta ti wọn n fun wa tẹlẹ ko to rara, a kan n fara daa ni."
Kemi tẹsiwaju pe, "awọn obinrin mii ma n fun ọmọ wọn ni ọmu nikan lai fi omi laa, to tumọsi pe, iru obinrin bẹẹ nilo isinmi ọlọjọ gbọrọ ki ara rẹ le padabọ sipo."

Oríṣun àwòrán, @GovUzodinma
Ni ti arabinrin Ogbuke, o ni idunnu ati ayọ nla ni iroyin isimi oloṣu mẹfa naa jẹ fun awọn obinrin Ekiti, nitori oṣu mẹta ti kere ju lati ṣe itọju ọmọ tuntun.
- "Òògùn ni wọ́n fi bò mí lójú tí mo fi bá ara mi láàrin àwọn ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn"
- Na òṣìṣẹ́ Amotekun, ko san ₦250,000 owó ìjìyà, ko sì tún fi ẹ̀wọ̀n oṣù kan jura
- Wọ́n yìnbọn pa àwọn tó fipá bá ọmọ ọdún 12 lòpọ̀ ní gbangba lẹyin ìdájọ́
- Ajínigbé méjì kàgbákò lásìkò tí wọ́n fẹ́ ẹ́ já ọmọ gbà lọ́wọ́ ìyá rẹ̀ l'Ondo
Ogbuke sọ pe isimi oloṣu mẹfa naa yoo fun awọn obinrin ni anfani lati fun ọmọ wọn lọmu fun oṣu mẹfa gbako lai si idiwọ iṣẹ.

Oríṣun àwòrán, @EKSDGs
Kọmiṣọna fun eto iroyin ipinlẹ Ekiti, Ọgbẹni Muyiwa Olumilua sọ pe idi ti Gomina ipinlẹ naa, Kayode Fayemi ṣe gbe igbesẹ ọhun ni lati mu aye dẹrun fun awọn eeyan ipinlẹ Ekiti.
Olumilua sọ fun BBC pe, ṣise afikun si akoko isinmi awọn abiyamọ naa yoo fun wọn lanfani ati sinmi si, ki ara wọn lee mokun daadaa ki wọn to pada sẹnu iṣẹ.
O ni, ṣe ni ijọba Ekiti n tẹle amọran awọn eleto ilera to sọ pe, o yẹ ki iya ọmọ fun ọmọ jojolo lọmu fun oṣu mẹfa, leyi ti yoo nira lati se, ti wọn ba wa lẹnu iṣẹ.












