Ecuador: Nàìjíríà yóò má a wọ Ecuador láì gba ìwé ìrìnà

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Orilẹ-ede Naijiria ati Ecuador ti se adehun ti yoo fun awọn ọmọ orilẹ-ede Naijria ni anfani lati wọ orilẹede Ecuador lai gba iwe irinna.
Orilẹ-ede Ecuador wa ni ariwa-iwọ oorun South America, pẹlu Colombia ni apa ariwa nigba ti orilẹ-ede Peru si wa ni apa ila ati guusu orilẹ-ede naa.
Asoju ilẹ Ecuador si Naijiria, Arakunrin Deopoldo Rovayo, lo sọ eyi ni Abuja nigba ti o se abẹwọ si akọwe agba fun ile-isẹ okeere lorilẹ-ede Naijria, arakunrin Olukunle Bamgbose ni Ọfiisi rẹ.
Rovayo wi pe adehun naa yoo waye lati mu ibasepọ to gbooro wa laarin orilẹ-ede mejeeji, nitori yoo faye silẹ fun awọn ọmọ orilẹ-ede mejeeji lati wọle- jade lai si iwe irinna ti yoo da wọn duro.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Asoju orilẹ-ede Ecuador naa fikun pe, o le ni ẹgbẹrun kan ọmọ Naijiria to n gbe ni orilẹ-ede Ecuador, atipe iye wọn yoo ma a pọsi.
Ninu ọrọ tirẹ, Bamgbose fi da asoju ilẹ Ecuador loju wi pe Naijiria yoo sisẹ pọ pẹlu wọn lati mu adehun naa wa is imusẹ.









