Ọwọ́ tẹ pásítọ̀ àti àwọn èèyàn mìí lórí ikú akẹ́kọ̀ọ́ LASU l'Ekoo

Aworan Oloogbe Quadri Adedamola Ogunbode ati awọn to n hu oku naa

Oríṣun àwòrán, Sahara Reporters

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 4

Lẹyin ariwo iku ojiji to pa akẹkọọ-jade kan ni Yunifasiti ipinlẹ Eko (LASU), iyẹn Quadri Adedamola Ogunbode, ileeṣẹ ọlọpaa Eko ti hu oku naa l'Ọjọruu, ọjọ kejila, oṣu Kẹta, ọdun 2025.

Igbesẹ oku hihu yii waye lẹyin ti ijọba ti kọkọ ti ile ijọsin Sẹlẹ kan, Ileri Oluwa Parish, ti wọn ni ọmọkunrin naa ku si, pa.

Yatọ si hihu oku ati titi ṣọọṣi pa, ọwọ tun ba awọn eeyan mẹrin kan ti wọn ni wọn lọwọ ninu iku Oloogbe Quadri Ogunbode.

Ṣugbọn ki lo ṣẹlẹ gan-an ṣaaju awọn igbesẹ yii?

Quadri di awati lẹyin to dagbere ṣoọṣi

Lọjọ kẹrindinlogun, oṣu Kinni, ọdun 2025 ni Quadri, ẹni ọdun mejidinlọgbọn, di awati.

Iroyin sọ pe ọdọkurin to kẹkọọ gboye nipa oṣelu naa ti kọkọ ba ọrẹbinrin rẹ sọrọ lọjọ naa.

O n ba a sọrọ lọwọ pe oun n lọ si ṣọọṣi Sẹlẹ ti a mọ si Ileri Oluwa Parish, to wa ni LASU, ni o deede pari ipe naa, latigba naa ni ẹnikẹni ko si ti gbọ ohun rẹ mọ tabi ri laaye.

Whepetoji Babaniyeh ni wọn pe orukọ oluṣọ to n darii ṣoọṣi naa to ni oun fẹẹ lọọ ri.

Lẹyin eyi ni wọn kede rẹ bii ẹni to sọnu ti wọn si n wa.

Ọjọ kejidinlogun, oṣu Keji ni wọn yi ẹjọ naa kuro ni ti ẹni ti wọn n wa, ti awọn ọlọpaa kede pe iwadii lori iku Quadri lo yẹ ọrọ naa, lẹyin eyi ni wọn si pada ri ọna abayọ.

Wọn ri oku Quadri ninu koto ti ko jin

Alukoro ọlọpaa ipinlẹ Eko, Benjamin Hundeyin, fidi ẹ mulẹ fun awọn akọroyin, lọjọ Iṣẹgun, ọjọ kọkanla, oṣu Kẹta 2025, pe awọn ti ri oku oloogbe Adedamọla.

Gẹgẹ bi Ọgbẹni Hundeyin ṣe wi, afurasi akọkọ ninu iṣẹlẹ yii, Olaoluwa Ajisomo, lo mu awọn lọ sibi ti wọn sinku naa si, eyi si jẹ nibi ẹyin ogiri kan lagbegbe LASU.

Hundeyin ṣalaye pe ahesọ lasan ni iroyin to sọ pe inu ọgba ṣọọṣi ni wọn ti ri oku ọhun.

Lori idi ti wọn fi ti ile ijọsin naa pa, o ṣalaye pe olobo ti ta ileeṣẹ ọlọpaa pe, awọn kan fẹẹ dana sun ṣọọṣi naa lati gbẹsan iku to pa Quadri.

Ṣaaju ni wọn ti mu Oluṣọ Whepetoji Babaniyeh, wọn si pada mu Olaoluwa Ajisomo, iya rẹ; Omolara Ajisomo, lori ẹsun pe o ran awọn ọmọ rẹ meji, Teniola ati Olaoluwa Ajisomo, lọwọ lati sa lọ, lẹyin ti wọn ti kọwọ bọ apo ikowosi Oloogbe, ti wọn si ti gba 300,000 ẹnikọọkan nibẹ.

Wọn ni pasitọ paapaa gbowo ninu akanti oku

Skip podcast promotion and continue reading
Èyí ni ìkànnì Whatsapp wa

Àjáàbalẹ̀ ìròyìn BBC News Yorùbá lórí WhatsApp rẹ

Darapọ̀ mọ́ wa nibì

End of podcast promotion

Bi oloogbe Adedamola ṣe di awati ni awọn kan ti bẹrẹ si i gba owo jade lati inu akanti rẹ, lasiko ti awọn ẹbi rẹ ṣi n banujẹ lọwọ.

Ninu awọn ti wọn ni wọn gbowo lakanti naa ni wọn ti darukọ Olaoluwa Ajisomo, afurasi akọkọ ti wọn lo gba owo lakanti Oloogbe, nipa lilo foonu tiyẹn n lo ko too ku.

Alukoro Hundeyin lo ṣalaye eyi lọjọ Aje.

Bakan naa lo darukọ, Whepetoji Sunday, pasitọ ti wọn l'oun naa gba N70,000 lati akanti Oloogbe Quadri, ati Sheriff Adebayo,ara ṣọọṣi naa to gba ẹgbẹrun lọna ọọdunrun, (N300,000.)

Iroyin kan ti a ko fidi ẹ mulẹ, sọ pe owo to to 1.5m ni wọn gba ninu akanti naa, ati pe ọdọ Oluṣọ pẹlu awọn afurasi yooku ni owo naa wọlẹ si .

Ṣaaju iku rẹ, inu ọgba Fasiti LASU ni a gbọ pe oloogbe Quadri ti n ta awọn nnkan eelo ti awọn akẹkọọ nilo nile ẹkọ naa, o si n ri ti aje ṣe daadaa.

SP Benjamin Hundeyin, sọ pe iwadii ṣi n tẹsiwaju nipa iṣẹlẹ yii, bẹẹ ni afurasi akọkọ, Olaoluwa Ajisomo, ti jẹwọ ohun to ṣe ninu nipa rẹ.

Hundeyin sọ pe gbogbo awọn to lọwọ si bi Oloogbe Quadri Adedamola Ogunbode ṣe di awati, bi wọn ṣe sare sin in ati bi owo ṣe n jade lakanti rẹ ni ọwọ yoo ba pata.

O fi kun un pe fun iwadii kikun ni awọn ṣe hu oku naa lẹyin tawọn ti mọ ibi ti wọn sin in si, ati pe ọpọ aṣiri ni yoo pada tu, ti awọn ẹlẹṣẹ ko si ni Iọ lai jiya.