Láàrin ọdún kan, àyípadà ńlá yóò wáyé ní Nàìjíríà - Shettima

Aworan

Oríṣun àwòrán, Facebook/Kashim Shettima

Igbakeji aarẹ orilẹede Naijiria, Kashim Shettima ti sọ pe ayipada gidi yoo de ba orilẹede Naijiria laarin oṣu mẹsan an si ọdun kan isẹjọba Aarẹ Bola Ahmed Tinubu.

Shettima ṣo eyi di mimọ niluu St Petersburg lasiko to n se ipade pọ pẹlu awọn ọmọ orilẹede Naijiria to n gbe ni Russia.

O wa fi awọn ọmọ Naijria lọkan balẹ, paapa awọn to n gbe ni Russia pe isẹjọba Tinubu yoo se isẹ takuntakun lati mu orilẹede Naijiria tẹsiwaju.

Skip Facebook post
Allow Facebook content?

This article contains content provided by Facebook. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Facebook cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: The BBC is not responsible for the content of external sites.

End of Facebook post

"Mo n fi dayin loju pe laarin oṣu mẹsan si ọdun kan, iyatọ nla yoo waye lorilẹede Naijiria.

"Mo n sọ eleyi nitori mo gbagbọ ninu isẹjọba Aarẹ Tinubu."

Shettima ni ijọba to wa lode bayii n sa apa rẹ lati mu ayipada nla ba ọrọ ajẹ, eyi to ni yoo fun awọn ileeṣẹ olokun lati wa si orilẹede Naijria.

Bakan Igbakeji aarẹ ni oun lero lati pese eto ẹko fun awọn Naijria toto milọnu kan lori Ayelujara.