Lai Mohammed: Mi ò mọ ohunkóhun nípa àbádòfin ọ̀rọ̀ ìkórìíra

Lai Mohammed

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, O sọ pe ko si abadofin kankan nile igbimọ aṣofin Naijiria to ni ṣe pẹlu ọrọ ikorira

Minisita eto ibanisọrọ ati iroyin lorilẹede Naijiria Lai Mohammed ti sọ pe oun ko mọ ohunkohun nipa abadofin ọrọ ikorira.

Lai sọ ọrọ naa nibi ifọrọwerọ kan lori eto "Conflict Zone" pẹlu ileeṣẹ DW News to waye ni ilu London.

Nigba to n dahun awọn ibeere nipa abadofin to ni ṣe pẹlu titẹ oju ẹtọ awọn ọmọ Naijiria mọlẹ lati sọrọ lori itakun agabye, o ni oun ko mọ nnkan kan nipa abadofin naa.

Lai tẹsiwaju pe, ko si abadofin kankan nile igbimọ aṣofin Naijiria to ni ṣe pẹlu ọrọ ikorira tabi ṣiṣamojuto oju opo ayelujara.

O sọ pe orilẹ-ede Naijiria ko fun awọn oniroyin lọrun lati sọrọ bo ṣe wuwọn ati pe, ijọba to wa lode ko tẹ oju ẹtọ awọn ara ilu mọlẹ.

O ni "Mo ti jẹ Ministia fun nnkan bi ọdun marun un bayii, mi o tii ri eto kan ti ijọba yii ṣe to jẹ lati fi ẹtọ ara ilu dun wọn."

Minisita naa sọ pe ijọba Buhari ko ni ohunkohuin lati fi pamọ, ati pe ijọba naa n dari ilu gẹgẹ bi ofin ṣe gbe kalẹ.

O tẹsiwaju pe irọ nla ni pe ijọba ko fọwọsowopọ pẹlu awọn ajọ ajafẹni ni Naijira ati kaaakiri agbaye.

Ṣaaju ni ọgbẹni lai ti sọ fun awọn oniroyin pe ijọba yoo maa ṣamojuto oju opo ikansiraẹni lori itakun agbaye.

Lẹyin ti fidio ifọrọwerọ naa jade tan ni ọpọ awọn ọmọ Naijiria bẹrẹ si n fi eroungba wọn lede loju opo Twitter.

Àkọlé fídíò, 'Ọwọ́ tó bá dilẹ̀ ni èṣù ń bl ní iṣẹ́kíṣẹ́'