Iwoye Ketu taboo: Òrìṣà kò faramọ́ ká gbìn àlùbósà tàbí ká ló aburada
Ìdálùú kúkú ni ìṣèlú....
Owe Yoruba kan ni 'Bi a se n se ni ile wa, eewọ ibo miiran ni'.
Gbogbo ilẹ Yoruba lo ni eewọ kan tabi meji ti wọn ni igbagbọ pe o le sokunfa ifasẹyin si ilẹ wọn.
Bi wọn ko se ki n jẹ aja ni awọn agbegbe kan, ni wọn ko si ki n jẹ ejo ni awọn agbegbe miiran sugbọn ni ilu Iwoye Ketu, wa ni ijọba ibilẹ Imeko Afon ni ipinle Ogun.
Won wa ni aarin Naijiria ati Orile Ede Republic of Benin ni Iwo Oorun Guusu ni ilẹ Naijiria ni le Adulawo eewọ ti wọn yani lẹnu pupọ.
- Akinwumi Isola dárà nínú ìwé "Nítorí Owó" lórí Akomolede Yoruba
- Mọ̀ sí i nípa Oba Yesufu Asanike, Olubadan tí kìí fi ọ̀rọ̀ sí abẹ́ ahọ́n sọ kódà níwájú sọ́jà
- Wo bí wọ́n ṣe sin Ọba Satani pẹ̀lú ọkọ̀ àti orin tó fẹ́ràn jù
- Ìdí tí wọn kii fi jẹ́ kí obìnrin jẹ Ọ̀ọ̀ni ni Ile Ife
- Àsìkò wo ló yẹ kí obìnrin bẹ̀rẹ̀ ìbálòpọ̀ padà lẹ́yìn ìbìmọ láìséwu?

Oríṣun àwòrán, Olubusola Afolayan
Ibo ni Ilu Iwoye Ketu?
Iwoye Ketu je ilu kan to wa ni ala laarin orilẹede Naijiria ati otilẹede Benin. Ilu yii wa labẹ ijọba ibilẹ Imẹkọ Afọn nipinlẹ Ogun.
Olumu ti ilu Imoye Ketu, Oloye Emmanuel Sunday Babatunde ba BBC News Yoruba sọrọ, o ni pe ilu Ile Ife ni awọn baba nla wọn ti sẹwa lati wa di ilu Imoye Ketu silẹ

Kini awọn eewọ Imoye Ketu?
Olumu ti ilu Imoye Ketu ni Imoye ni eewọ to pọ, to si se koko ki awọn ọmọ ilu yago fun eewo naa.
Lara awọn eewọ ti Olumu sọ ni pe wọn ko ni anfani lati sin Ẹlẹdẹ ni ilu Imoye.
Bakan naa, eewọ ni pe ki awọn araalu lo aburada lati bo ori wọn lasiko ti ojo ba n rọ tabi ti oorun ba ran.
Ikẹta ni Olumu darakọ pe o jẹ eewọ ni pe wọn ko gbọdọ gbin Alubọsa niluu Imoye.
Oloye Emmanuel Sunday to n dari Iwoye Ketu jẹ Olumu, Won ni Orisa Oluwa eyi ti Imoye gbagbọ pe o jẹ alaabo fun Baba nla wọn ko rira ohun idọti, ti pupọ si ri Ẹlẹdẹ gẹgẹ bi ohun idọti.
Olumu salaye, ilẹ kun, ẹ wọ fidio yii lati mọ si nipa Ilu Imoye Ketu ati awọn eewọ wọn.
- Wo ìtàn bí ààlọ́ ṣe bẹ̀rẹ̀ àti onírúurú ààlọ́ àpagbè àti àpamọ̀
- Mọ̀ síi nípa ewu tó rọ̀ mọ́ níní ìbálòpọ̀ lásìkò ìlóyún lórí ètò Sé lóòtọ́ ní BBC
- Àwọn Olùkọ́ Yorùbá ní ìpínlẹ̀ Osun ṣe bẹbẹ lórí ètò Akomọlede àti Aṣa lórí BBC
- Igi ẹ̀fọ́, ojú ẹlẹ́gba àti oríṣi orúkọ̀ míì ní wọ́n ń pè mí nítorí pé Òbí mi kọlà sí ojú mi- Damilola