Iriri agba: Ojogbon Ayodele Desalu : Nǹkan tójú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Nàìjíríà ń rí lókè òkun kọjá àfẹnusọ

Àkọlé fídíò, Ohun tí ojú àgbà rí tí ojú àgbà fi jìn, bí ọmọdé bá rí i ó ṣeéṣe kí ojú náà fọ́ pátápátá.

Yorùbá bọ̀ wọ́n ní ohun tí ojú àgbà rí tí ojú àgbà fi jìn, bí ọmọdé bá rí i ó ṣeéṣe kí ojú náà fọ́ pátápátá.

Ọ̀jọ̀gbọ́n Ayodele Desalu tí ilé ẹ̀kọ́ gíga fásitì ìlú Ibadan nígbà tó ń BBC Yorùbá sọ̀rọ̀ nípa ìrírí wọn lẹ́nu ẹ̀kọ́ kó tí wọ́n sì rò lórí àwọn nǹkan tí ojú wọ́n rí kí wan tó dé ipò tí wọ́n wà lónìí.

Ọ̀jọ̀gbọ́n Desalu ṣàlàyé pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹlẹ́kọ̀ọ́ ni àwọn òbí òun síbẹ̀ ọ̀pọ̀ ìgbà ni òun tún kíláàsì kan ní ẹ̀ẹ̀mejì ó kéré tán nígbà tí òun fi wà lẹ́nu ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àmọ́ àìkó àárẹ̀ ọkàn ní òun fi di Ọ̀jọ̀gbọ́n lóde òní.

Ó ní pé ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n bá dé òkè òkun ni wọ́n máa ń ṣe dáadáa àti pé ọ̀pọ̀ nǹkan tí ojú akẹ́kọ̀ọ́ Nàìjíríà máa ń rí nílẹ̀ òkèrè kò kéré rárá.