Ayo Adebanjo: Èèkàn Afenifere ní kìí ṣe Tinubu ló kọ́ ilé fún òun gẹ́gẹ́ bí Bisi Akande ṣe sọ

Oríṣun àwòrán, Bola Tinubu
Olórí ẹgbẹ Afenifere, alagba Ayo Adebanjo ti sọ pé owo ti oun ya ni banki ni oun fi kọ ilé òun to wà ní Lekki, kii ṣe oloye Bola Tinubu lo kọ ile náà fún òun.
Adebanjo lo sọ ọrọ naa nínú atẹjade kan to fi ṣọwọ sí àwọn akọroyin ni ìdáhùn sí ọrọ alagba Bisi Akande ninu iwe rẹ, eyiti o sọ pe Tinubu lo kọ ile Adebanjo to wa ni Lekki fun un.
Adebanjo si tun sọ pe ki Akande kan si EFCC lati ṣe iwadi ọrọ́ toun sọ to ba da a loju.
- Idán oríta nínú ṣọ́ọ̀ṣì Winners Chapel, okùnrin kan kù gììrì mọ́ Bíṣọ́ọ̀bù Oyedepo lórí pẹpẹ ìwàásù
- Èmi àti ọmọ ẹgbẹ́ akọrin wa jọ yó ìfẹ́ ara wa ni - Pásítọ̀ ní òun kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìfipábáni lòpọ̀
- Àtúntò Nàìjíríà ni mo tò fún o, ìdí tí ẹ ṣe ní láti gbọ́ sí àwọn tó ń jà fún Yoruba Nation lẹ́nu rèé - Sẹnetọ Olujimi
- Wo ibi tí wọ́n ti ń sun ẹran èèyàn jẹ bí ẹran ìgbẹ́ ní ìpínlẹ̀ Imo
- Ta ni Ọba Sátánì tó fẹ́ ìyàwó 57 kó tó jáde láyé lẹ́ni ọdún 74?
- Ìròyìn òfegè lásán ni! Ilé ẹjọ́ kò gba agbára lọ́wọ́ àwọn ibùdó ìgbéyàwó tí a dá sílẹ̀, ẹ m'ẹ́nu kúró lórí Ikoyi Registry
Atẹjade náà ni "Ni ọsẹ kan sẹyin, wọn sọ níbi tí wọn ti ṣe ìfilọ́lẹ̀ iwe ti oloye Bisi Akande kọ pe mo ke sí Bola Tinubu lati kọ ilé fún mi.
"Niwọn igba ti Tinubu fúnra rẹ wà níbí ìfilọ́lẹ̀ ìwé náà, mo gbagbọ pe o yẹ kó ti sọrọ pe kò sí ootọ kankan ninu ọrọ naa."
Adebanjo sọ pé bó tilẹ jẹ pé Tinubu fúnra rẹ ti sọ ṣaaju pe oun ko ipa ribiribi ninu bi Tinubu ṣe di gomina nipinlẹ Eko, oun ko figba kankan tọrọ owo lọwọ rẹ ri, anbelete pe o kọ ilé fún òun.
Baba Adebanjo ni awọn èèyàn oun ko fẹ kí òun fún Bisi Akande lesi lórí ọrọ naa, ṣugbọn oun yan láti fèsì ki Akande ma lọ ro pe ọlọgbọn ni o n ṣe.
Gẹgẹ bíi ohun tó sọ, ile rẹ to wa ní àdúgbò Nuru Oniwo, ìyẹn ni Àgùdà Surulelre ni oun n gbe ki oun to ko lọ sí Lekki.
O ni "Ile ifowopamọ GTB ni mo ti ya owo ti mo fi parí ilé mi to wa ni Lekki, eyiti mo n gbe báyìí.
"Lẹyin naa lo ké sí àjọ EFCC lati wa yẹ idi oro oun wo.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
O tun ké sí Bisi Akande lati sọ okodoro ọrọ nipa oun to ti kọkọ sọ ṣaaju pe Tinubu lo kọ òun.















