Senator Olujimi on Yoruba Nation: Ẹ wo Sẹ́nétọ̀ obìnrin tó gbàgbọ́ nínú àtúntò Nàìjíríà àti ìjà fún ìyapa Nàìjíríà

Àkọlé fídíò, BBC News: Ifọrọwerọ pẹlu Sẹnẹtọ Olujimi

"Olóore ni mo jẹ́ sí Fayose la ṣe le ṣiṣẹ papọ, ko si ija laarin wa".

Sẹnetọ to n ṣoju ẹkun Guusu Ekiti nile igbimọ aṣofin, Abiodun Christine Olujimi ti ni bo pẹboya, ko si igba ti awọn adari Naijiria ko ni gba si awn to n ja fun ẹtọ wọn lẹnu.

Bakan naa lo ṣalaye idi to fi dara ki awọn obinrin kopa ninu oṣelu.

O fi ara rẹ ṣe apẹrẹ gẹgẹ bo ṣe n ṣoju ẹkun kan l'Ekiti to jẹ ilu baba rẹ.

"Too ba fẹ dupo, wọn a ni ilu ọkọ ẹ ni koo lọ, boo ba tun lọ si ilu ara rẹ, awọn naa a ni ṣebi o lọkọ. Ọpẹlọpẹ Ọlọrun ni mo ṣe wa ni ipo ti mo wa yii".

Arabinrin Olujimi tun ba BBC Yoruba sọrọ lori awọn to n ja fun Yoruba Nation ati ipo ti Naijiria wa lọwọlọwọ.

Àtúntò Nàìjíríà ni mo tò fún o, ìdí tí ẹ ṣe ní láti gbọ́ sí àwọn tó ń jà fún Yoruba Nation lẹ́nu rèé - Sẹnetọ Olujimi

O ni ilu le gan lasiko ti a wa yii ti gbogbo eniyan si n duro de asiko idibo to n bọ lati ṣe ipinnu to yatọ ti yoo mu aye wọn lọ siwaju.