Parent beats Teacher in Oyo: Ìjọba Oyo dá akẹ́kọ̀ọ́ dúró tórí ìyá rẹ̀ lu tíṣà

Oríṣun àwòrán, Screen Shot
Akẹkọọbinrin ile ẹkọ girama Jericho niluu Ibadan ti gba idaduro lẹnu ẹkọ rẹ lori ẹsun pe o ko awọn ẹbi rẹ lọ si ile ẹkọ, nibi ti wọn ti fiya jẹ akẹgbẹ rẹ kan at'awọn olukọ rẹ pẹlu.
Kọmiṣọnna feto ẹkọ nipinlẹ Oyo, Ọgbẹni Rahman Abiodun Abdu-Raheem lo sọrọ yii ninu atẹjade kan to fi sita niluu Ibadan.
Kọmiṣọnna eto ẹkọ ni laipẹ yii ni iya akẹkọọbinrin naa yabo ilẹ ẹkọ rẹ pẹlu awọn tọọgi ti wọn sì bẹrẹ si ni lu awọn eeyan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wo àwọn ìdí tí Adájọ́ fi dá Wòlìí Sotitobire láre, tó sì da ẹ̀wọ̀n gbére nù
- Akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún ló wọlé lu ọmọ mí tó fi kú, kìí ṣe bọ́ọ̀lù ló gbá - Baba akẹ́kòó Dowen fèsì
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá kéde ìgbaniṣíṣẹ́ fáwọn àkàndá ẹ̀dá
- Ìjọ Redeem gbé ojú òpó olólùfẹ́ kalẹ̀ sórí ayélujára fáwọn ọ̀dọ́ láti pàdé ọkọ tàbí aya
- Òfo ni 'White Paper' Sanwo-Olu kò sí ǹkan tó n jẹ́ bẹ́ẹ̀ lábẹ́ òfin - Adegboruwa
- Àwọn ọ̀dọ́ Eruwa ṣe ìwọ́de lórí ikú Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura ní Ife
- Wo orílẹ̀èdè tí ẹ̀dà Covid-19 tuntun Omicron rápálá wọ̀ l‘Áfíríkà
- Èsì iléẹ̀kọ́ Dowen rèé sí ìkú akẹ́kọ̀ọ́ tí àwọn òbí rẹ̀ ní àwọn ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn pa nítorí kò darapọ̀ mọ́ wọn!
Kọmiṣọnna ṣalaye pe awọn tọọgi ọhún lu akẹkọọkunrin kan, awọn olukọ at'awọn at'awọn obi nibi ti ìpàdé obi ti n waye.
O sọ fun BBC Yoruba pe gbogbo awọn ti ọrọ kan lóri iṣẹlẹ naa ni ijoba yoo kan si lati le ri pe iru rẹ ko waye mọ lọjọ iwaju.
Ọgbẹni Abdu-Raheem rọ gbogbo eeyan lati ni ẹmi ikonimọra, iṣọkan ati ibọwọ fun ara ẹni.
Kọmiṣọnna eto ẹkọ tun sọ pe ijọba ipinlẹ Oyo ko ni fi oju ire wo ẹnikẹni to ba n hùwa jagidijagan.
Bakan naa ni o rọ awọn obi, akẹkọọ ati gbogbo awọn ti ọrọ kan lati gbaruku ti eto ẹkọ to yanranti.





















