ILana Omo Oodua: Ẹgbẹ́ IOO jáwé gbélé ẹ fún Otunba Olukoya, fòǹtẹ̀ lu Adeleye àti Akinwande

Oríṣun àwòrán, other
Ẹgbẹ Ilana Omo Oodua to n beere fun idasilẹ orilẹede iran Yoruba ti salaye nipa awọn ohun to fa awuyewuye to n waye ninu ẹgbẹ naa.
Ninu atẹ́jade kan ti ẹgbẹ naa fi sọwọ si BBC Yoruba, o ni oun ti ja ewe gbele ẹ fun Otunba Folasade Olukoya, tii se ọkan lara awọn asoju rẹ ninu ẹgbẹ ajijagbara fun iyapa Naijiria lapapọ, NINAS.
Bakan naa ni ẹgbẹ ọhun tun ṣalaye ninu atẹjade naa pe, Ọgbẹni Maxwell Adeleye ati Dokita Kayode Akinwande yoo si maa tẹsiwaju pẹlu ipo wọn lati ṣoju Ilana Omo Oodua ninu ẹgbẹ NINAS.
- Buhari, dẹ̀yìn lẹ́yìn Sunday Igboho, Akintoye àti Kanu- Ẹgbẹ́ ọmọ Yorùbá kìlọ̀
- Akintoye àti èèyàn 1m míì ń lọ àpéjọ UN lórí ìyapa Nàíjíríà
- Àwọn alamí ìjọba kan ti wà láàrín àwa ajìjàgbara Yoruba Nation tó ń bínú pé Sunday Igboho ti ga ju àwọn lọ - Akintoye
- Wọ́n yọ Nàìjíríà kúrò lára àwọn orílẹ̀èdè alákatakítí ẹ̀sì lágbàáyé, ọ̀pẹ́ Buhari sí Anthony Bliken rèé
- Mi ò pààyàn rí láyé, mi ò kí ń ṣe afini ṣòògùn owó, ẹ jọ̀wọ́ dúró dé ìwádìí Ọlọ́pàá - Rahmon Adedoyin tó ni hòtẹ́ẹ̀lì
- Kanpe ni òkú Timothy Adegoke wà, wọn kò gé ẹ̀yà ara rẹ̀ - Ọlọ́pàá Osun
- Ìrìn-àjò ìfẹ́ wa kò tíì bẹ̀rẹ̀ nígbà tí mó ní Lateef Adedimeji kìí ṣe ọ̀rẹ́kùnrin mi- Mo’Bimpe
Ọjọgbọn Banji Akintoye to jẹ aarẹ Ilana Omo Oodua ni alaga ẹgbẹ NINAS ni Naijiria.
Ṣaaju ni Ọgbẹni Tony Nnadi, Esq to jẹ akọwe ẹgbẹ ajijagbara LNC (Lower Niger Congress) sọ pe Ọgbẹni Adeleye ko si lara awọn aṣoju ẹgbẹ Ilana Omo Oodua ni NINAS mọ.
Ṣugbọn ẹgbẹ naa daa pada pe ko si ohun to jọ bẹẹ, ati pe awada kẹri kẹri ni ọrọ naa.
Wọn Ọgbẹni Adeleye si ni agbẹnusọ Ọjọgbọn Akintoye ati fun ẹgbẹ Ilana Omo Oodua.
Amọ, ẹgbẹ IOU ṣalaye ninu atẹjade ti wọn sita pe Otunba Olukoya kii ṣe aṣoju awọn mọ ninu ẹgbẹ NINAS nitori o ti fi ẹgbẹ naa silẹ.
Wọn rọ awọn ẹgbẹ ajijagbara mii lati mọ bayii pe Otunba Olukoya kii ṣe aṣoju ẹgbẹ OOU mọ.
''A n fi akoko yii sọ fawọn eeyan pe Ọgbẹ Nnadi ko le maa la le wa lọwọ ninu ẹgbẹ IOU.
A rọ Ọgbẹni Nnadi lati gbaju mọ ohun ti o ka an, ki o ye sọrọ gẹgẹ bi alatako iran Yoruba.
Akojọpọ ẹgbẹ ajijagbara fun orilẹede tuntun ni ẹgbẹ NINAS jẹ, kii ṣe Nnadi lo ni ẹgbẹ naa.
Lakotan, a fi ọntẹ lu Ọgbẹni Adeleye ati Dokita Akinwande gẹgẹ bi aṣoju wa nitori wọn fihan pe ọmọ Yoruba atata ni wọn jẹ.
A o maa kede ẹni ti yoo rọpa Olukoya gẹgẹ bi ọkan lara aṣoju mẹta ti a ni ninu ẹgbẹ NINAS,'' ẹgbẹ IOU lo ṣalaye bẹẹ.
Ogun ọmọ ẹgbẹ IOU to fi mọ Ọjọgbọn Akintoye gan an lo buwọlu atẹjade naa.


















