Fulani herdsmen: Oba Soun ló fí mi jẹ ọba Sabo ni Ogbomọṣọ- Alh Haruna Bala Abdulsala

Àkọlé fídíò, Fulani-Yoruba Crisis: Oba Soun ló fí mi jẹ ọba Sabo ni Ogbomọṣọ- Alh Haruna Bala Abdulsala

Bi ọgọrun un ọdun sẹyin ni Baba baba wa jẹ ọba Sabo akọkọ ni Ogbomoso- Oba Sabo Haruna

Olorun ló di ìran Yorùbá, Hausa àti Igbo papọ̀- Oba Sabo ní Ogbomoso

BBC ṣabẹwo si Alahaji Haruna Bala Abdulsalami to n dari Sabo ni Ogbomoso nipinlẹ Oyo ni guusu Iwọ oorun Naijriia.

Oba Sabo

Oba Sabo yii sọ itan bi awọn baba nla rẹ ṣe de Ogbomọsọ ki wọn to jẹ Oba nibẹ.

O ṣalaye ipa pataki ti Oba Soun Ogbomoso ko ninu sisọ oun di ọba ni Sabo.

Oba Sabo ni Oba soun sọ pe ki oun maa dari gbogbo ẹya eeyan to ba ti n gbe ni Sabo ni Ogbomọṣo.

Oba Sabo

Bakan naa ni Oba Haruna Bala Abdulsalami sọ fun BBC Yoruba pe ewe lo n daabo bo ẹkọ ni ọrọ Hausa ati Yoruba.

O ṣakawe pe bi Yoruba ṣe pọ nilẹ Hausa ti wọn ko si fẹ wale mọ naa ni Hausa pọ nibi to ti ṣori rẹ.

Oba Sabo

Koda, O ni Yoruba ni iyawo oun gan an.

Oba Haruna Bala Abdulsalami ni ija Fulani, Hausa ati Yoruba ko jẹ tuntun rara.

Nitori pe o ti wa tipẹtipẹ.

O ni ẹya Fulani fẹ fi gbogbo ọna gbe ogo ẹya wọn ga ni.