Yollywood Yemi Shodimu sọ̀rọ̀ pé àṣìlò ẹ̀bùn kò jẹ́ kí Nàìjíríà dàgbà sókè mọ́

Oríṣun àwòrán, Facebook/Yemi Shodimu
Odu ni o jẹ lagbo oṣere tiata ni Naijiria kii ṣe aimọ f'oloko.
Bi eeyan ba ti wo awọn ere ileeṣẹ sinima Mainframe ni nkan bi ọdun meloo kan sẹyin, yo ranti arakunrin kan to kopa ribiribi ninu awọn ere ti Tunde Kelani dari wọnyi.
Yemi Shodimu lẹni taa n wi to si kopa ninu awọn ere sinima bi Ò le kù (1997), Ti oluwa ni ile (1993) ati Kòseégbé (1995).
BBC News Yoruba gba lalejo loju opo Facebook Live ti o si yanana ọrọ lori awọn ohun to ni ṣe pẹlu ere sinima ni Naijiria.
Diẹ lara awọn ohun t ri fayọ ninu ifọrọwerọ naa ree:
Ifarada pọ fawa oṣere nigba ta fi n kopa ninu ere sinima yatọ si tode oni
Gẹgẹ bi agba ọjẹ oṣere sinima yi ti ṣe ṣalaye, o ni tifẹtifẹ, tọkantọkan lawọn fi n se ere sinima lasiko tawọn.
O sọ pe awọn alakoso nigba naa ki ṣe alayaba.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
''Inu ọkan wọn ni itan ti wọn ba kọ ti maa n wa ati pe ẹkọ ti wọn kọ nipa gbigbe itan silẹ ni wọn n lo.''
Ẹbun pataki, ẹbun nlanla ni Tunde Kelani jẹ fun orileede Naijiria
Lori gbajugbaja oludari ere sinima yi, Yemi Shodimu ni o ṣeni laanu pe awọn to yabara ti wa pọ ninu ere sinima.
O ni ṣugbọn kii ṣe lagbo osere tiatia nikan ni wọn wa bii kii se pe wọn pọ ninu oṣelu ati awọn iṣẹ miran ni Naijiria.

Ninu awọn nkan to sọnu ninu ere sinima ode oni, o sọ pe ti a baa n tiraka lati sọ itan oyinbo fun oyinbo, a ko le tẹsiwaju.
O ni aṣeyege pọ, kudiẹkudiẹ naa pọ to fi mọ awọn nkan aṣa wa to pọ ti a ko ti fi han fun araye ninu sinima.
''Ohun to n ṣe oyinbo loyinbo n kojọ ninu fiimu, ki lo de ti a wa naa ko gbe tiwa jade faraye gbọ?
O tẹsiwaju pe ''A ko ti bọ kuro ninu a n fi owo kun owo epo, owo ina, ki laa jẹ, ki laa mu, awọn nkan to n jo wa bi ina labẹ aṣọ pọ ti a gbọdọ fi han agbaye.''
Nipa isọkan Yoruba ati ọrọ iṣelu:
Sodiumu ni Yoruba ni lati pawọpọ ti wọn ba fẹ jana.
Shodimu yabara labẹ akori ọrọ yi lati sọ nipa oselu to n lọ lọwọ ni Naijiria
O sọ pe awọn to dantọ lati se oselu pọ ni Naijiria,bẹẹ lawọn ti ko yẹ ki wọn sunmọ oṣelu naa wa nibẹ.
O wa fi kun pe abaabọ fifi awọn ti ko yẹ sipo ni Naijiria n ba finra bayi.
''A feran lati maa ṣadura lori gbogbo nkan ni Naijiria ṣugbọn ọlọrun ma jẹ ki ọrọ wa ṣu Ọlọrun.
Asilo ẹbun wa ninu nkan to n ṣe wa ni Naijiria ti a ko fi dagbasoke''
- Wo àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ máleègbàgbé tó ṣẹlẹ̀ lágbo erè ìdárayá Nàìjíríà lọ́dún 2022
- Ṣé lóòtọ́ ni gómìnà Adeleke dìgbájú lu òṣìṣẹ́ DSS, tí wọ́n fi kó gbogbo ẹ̀ṣọ́ aláàbò rẹ̀ kúrò-
- Ọmọ ọdún mẹ́rìndínlógún dèrò àtìmọ́lé lẹ́yìn tó bú gómìnà ìpínlẹ̀ Yobe lórí ayélujára
- Tọkọtaya wọ “jẹsí” Messi àti Mbappe lọ́jọ́ ìgbéyàwó
- Ọkọ mi máa ń fún mi lóògùn orun lálaalẹ́ kó tó fipá bá ọmọ tó ń gbé lọ́dọ̀ mi lòpọ̀ - Ìyàwó Doctor Olaleye
- 2023- Kò ni sí àyè fún fóònù lílò nínú ojúkòó ìdìbò, ìdí rèé – INEC

















