Coronavirus in Nigeria: Esì àyẹwò ọmọ ati ìyáwọ ọmọ Atiku ti jáde

Oríṣun àwòrán, Others
Ninu atẹjade ti ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Bauchi fi sita ni a ti rii pe oun nikan ni aarun naa mu laarin awọn mẹfa ti wọn jọ kọwọrin.
Wọn ṣalaye pe iwadii ti fidiẹmulẹ pe awọn ọmọ ati ẹbi rẹ wa ni alaafia lai ni aarun coronavirus.
Ajọ NCDC si ti gbe igbesẹ to yẹ lati ya gomina Bala muhammed sọtọ bayii ki o ma baa le tan aarun naa kalẹ.

Oríṣun àwòrán, Bauchi
Gomina Bala Muhammad yii lo ti figa kan jẹ minista fun olu ilu Naijiria, Abuja ki o= to dije dupo gomina ipinlẹ Bauchi.
Ẹ wo ǹkan to sẹlẹ̀ sí ọmọ àti ìyàwó ọmọ Atikú tó lùgbàdì ààrun Coronavirus

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ìdúnú subú láyọ fún ẹbi àtikù nígbà ti èsì ayẹwò Coronavirus ìyáwó ọmọ Atiku àti ti àwọn ọmọ jáde ti wan ko si ni ààrun náà.
Ọmọ Atiku Mohammed ti wọ́n fi si ipamọ ni ilé ikwosan ikọni to wà ni Gwagwalad nilú Abuja nítori pé àyẹwo fi han pé o ni ààrun Coronavirus lọ́jọ́ Aiku.
Mohammed fẹ Badriyya to jẹ ọmọ gomina Bauchi Ahmed Muazu to tun jẹ alága ẹgbẹ́ òṣèlú PDP tẹ́lẹ ri.
Lásìkò to n ba àwọn onírolyin sọ̀rọ̀ ọgbẹni Zakari Aliyu to jẹ igbakeji alaga ilé igbé rẹ sàlàyé pé ko si ibẹru bojo nítori pe ẹbi ẹni ti wọ́n n sọrọ gan ko ni ààrun náà.
Aliyu ni " ọkunrin ti wan gbé lọ ni dédé àgo kan oru yẹn ni à[run Coronavirus, sùgbọ́n ìyáwó àwti àwọn ọmọ rẹ ko ni, sùgbọ́n o àwọn náà yóò wà ni igbélé fún ọjọ mẹrinla, mo si dúpẹ lọ́wọ́ ìyàwó rẹ pe o fọwọsowọpọ pẹlu wá".
Ọmọ Atiku ni ìròyìn sọ pé o de láti orilẹ̀-ède Switzerland si orill-èdè naijiria ti o si jẹ ọkàn lára àwọn orilẹ̀-è[de ti o n bààrun Coronavirus fira
Mò n lọ fun ìgbélé nítori mo ṣe alábapàdé ọmọ Atiku- Gomina Bauchi
Gomina ìpínlẹ̀ Bauchi, Bala Muhammed ti kéde pé òun náà yóò lọ fi ara òun si ìgbélé, lẹ́yìn ti ìgbákeji ààrẹ àná lórilẹ̀-èdè Naijiria fi léde pé pé ọmọ oun ti lugbàdi ààrun Coronavirus.
Gómìnà ìpínlẹ̀ Bauchi sàlàyépé òun àti ọmọ Atiku 'sun pàde àra àwọn nínú ọkọ bàlú láti ilú Eko lọ si ilú Abuja ti àwọn si bọ ara àwọn lọ́wọ́
Oludári ilé iṣẹ́ radio naijiria nígbà kan ri Ladan Salihu fi idí èyí mull lori àtẹjiṣẹ́ twitter rẹ̀ pé gbogbo àwọn ti àwọn ba ọmọ náà rin irin ajò ni àwọn ti lọ fi ara àwọn pamọ.
O ní àwọn ti fi ara àwọnnkalẹ fun àyẹwò báyìí ti àwọn si ni ìgbàgbọ́ pé akan ni èsì rẹ yóò jásí.
Nínú àtẹjjáde kan ti Gomina Bauchi fi sita láti ọwọ olùrànlọ́wọ́ pàtàkì rẹ lórí iròyìn Mukhtar Gidado, sàlàye pé àwọn jọ wó ọkọ ofurufu Aero Contractor ní to sì jẹ́ri si pé wọ́n jọ bọ́wọ lọ́ja náa.
Gómina ko fi àmì kankan hàn báyìí, bákan náà losi ti wọ́gile gbogbo àwọn ìpáde to yẹ ki o ní.
Coronaviris in Nigeria: Ọmọ Nàìjíríà kan ẹni ọdún 67 tó kó àrùn COVID-19 ti di olóògbé

Oríṣun àwòrán, Twitter/Federal Ministry of Health
Ọmọ Naijiria kan ẹni ọdun mẹtadinlaadọrin ti jẹ Ọlọrun ni pe lẹyin to lugbadi arun corona virus.
A gbọ wi pe ọkunrin naa ṣẹṣẹ rinrin ajo de lati ilẹ Gẹẹsi ni ki o to tẹri gbaṣọ ni Naijiria.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Ajọ NCDC ṣalaye loju opo Twitter rẹ pe ọkunrin naa ti ni awọn aisan kan lara tẹlẹ bi arun itọ ṣuga ati arun ti oloyinbo n pe ni Myeloma.
O jẹ ọmọ ọdun mẹtadinlaadọrin.
Atẹjade ajọ WHO sọ pe O ṣẹṣẹ de pada lati ilẹ Gẹẹsi laipẹ yii nibi to ti lọ ṣe itọju aisan ara rẹ.
Wọn ni ko pẹ to gba itọju "Chemoteraphy" tan nile iwosan nilẹ Gẹẹsi to fi pada wa sile.
- Ẹlòmíràn tún ti lùgbàdì àrùn Corona Virus nílùú Abuja àti Eko
- Ijọba ìpínlẹ̀ Eko àti Kwara ti kéde konile o gbélé
- Ìgbésẹ̀ ìjọba láti kojú àrùn coronavirus ń pani lẹ́rìn ín- Pásítọ̀ Adeboye
- Báwo ni àrùn coronavirus ṣe ń wọ Nàìjíríà
- Ìjọba ti pápákọ̀ òfúrufú Eko àti Abuja pa nítorí coronavirus
- Ijọba ìpínlẹ̀ Ogun dá sẹria f'àwọn aláigbọrọ jófin
Wọn ni o ti n gba itọju lori awọn aisan naa ki arun COVID-19 to mu lọ.
Ajọ NCDC kẹdun pẹlu idile oloogbe naa.
O ti di eeyan mẹrindinlogoji to ni ni arun naa ni Naijiria bayii ninu eyi ti awọn meji ti jade nile iwosan.
Ọmọkùnrin mi ti kó coronavirus, ẹ bá mi fi sínú àdúrà yín- Atiku
Ẹ fi adura ranmi lọwọ nitori ọmọkunrin mi ti lugbadi arun coronavirus to n tan kalẹ kaakiri agbaaye bi ina inu ọyẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Atiku Abubakar
Oludije fun ipo aarẹ fẹgbẹ oṣelu PDP, Atiku Abuabakar lo fọrọ yii lede loju opo Twitter rẹ lalẹ ọjọ Aiku.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Atiku ṣalaye pe oun ti sọ fun ajọ to n gbogun ajakalẹ arun ni Naijiria, NCDC, ati pe ọmọ naa ti n gba itọju nile iwosan olukọni fasiti Abuja to wa ni Gwagwalada.
''Inu mii yoo dun ti ẹ ba le fi ọmọ mi sinu adura yin, ki onikaluku rọra maa ṣe nitori otitọ ni pe arun coronavirus wa nita,'' Atiku lo sọ bẹẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 3
Atiku tun gboriyin fawọn oṣiṣẹ ile iwosan kaakiri orilẹede Naijiria fun iṣẹ takuntakun ti wọn n ṣe lasiko ajakẹlẹ arun covid-19 yii.
''Mo rọ gbogbo ọmọ Naijiria pe ki wọn maa mi kan ti a o fi ṣẹgun arun coronavirus ni Naijiria,'' Atiku lo woye bẹẹ.
Ọgbọn eeyan lajọ NCDC ti kede pe wọn ti ni arun coronavirus ni Naijiria, ninu eyi ti awọn meji ti ri iwosan.













