Yemi Osibanjo pàrokò ìkìlọ̀ ránṣẹ́ s'áwọn amofin àti adájọ́, ka ohun tó sọ

Yemi Osinbajo

Oríṣun àwòrán, @Yemi Osinbajo

Igbakeji aarẹ orileede Naijiria, Yemi Osinbajo ti kesi awọn onimọ ẹka idajọ lati se agbega ẹka idajọ Naijiria.

O fi ọrọ yi lede lasiko to n kopa nibi ayẹyẹ apejẹ ẹgbẹ awọn agbaọjẹ amofin ti won n pe ni: Body of Senior Advocates of Nigeria to waye nilu Eko.

Lasiko apejẹ yi, igbakeji aarẹ Osinbajo tẹnumọ pataki isẹ awọn amofin ati ipa ti wọn n ko nipa atunse awọn aisede lawujọ ati idagbasoke ilu.

''O ni eto idajọ wa dabi alumọni,kii se ti awọn to wa lẹka yi,kii se tawọn agbẹjọro tabi adajọ,ara ilu lo ni''

Kini Osinbajo tun so?

Ojogbon Yemi Osinbajo tun ni: 'Wọn n sanwo fun wa lati pese isẹ ti iwe ofin Naijiria gbe kalẹ nipa yiyanu aawọ ati mimu idajọ wa.

Alamojuto ni wa, awa kọ la nii. Igbakigba ti eto yi ko ba sisẹ bo ti se tọ tabi bo se yẹ,o tunmọ si pe a ti kuna lojuse wa.

Ojuse wa ni lati se atunse ti nkan ba ti dẹnukọlẹ''

Àkọlé fídíò, Buga Jesse

Bakan naa ni igbakeji aarẹ sọ pe ọna kan lati se idagbasoke eto idajọ Naijiria ni ki wọn mu agbega ba eto ẹkọ ẹka imọ ofin ki awọn to n bọ lẹyin baa le ri nkan dimu lọjọ iwaju.

"Gbogbo awa taa joko nibi loni la mọ nkan ti ko se deede pẹlu ẹka idajọ wa loni.Itan n kesi wa lati ri pe a se atunse rẹ''