Dudu Heritage Kò sí ń nǹkan tí ó ṣòro tó kí ènìyàn pàdánù ọkọ, Bimbo Oshin kọ ọrọ ìdárò lẹyin ikú ọkọ rẹ tó d'oloogbe

Oríṣun àwòrán, others
Gbajúgbajà òṣèré tíátà Bimbo Oshin tí padà sí ojú òpó ikansiraẹni instagram lẹ́yìn oṣù diẹ tó o ti n sọfọ ikú ọkọ rẹ Dudu Heritage
Ọkọ rẹ to kú ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹsàn-án ọdún 2021 tí ọ̀pọ̀ àwọn alabasisẹpọ rẹ sì jáde lójú òpó ikanairaeni láti wá kii kú ará fẹraku
Ìròyìn sọ pé wọn rí Ola Ibironke to jẹ́ ọkọ Bimbo Oshin to ṣubú lulẹ̀ ni ibi tí wón ti ń ṣe eré ìdárayá Gulf ni nnkan bí aago mẹjọ àbọ̀ ọjọ naa n'ilu Ibadan.
- Ta ni Ola Ibironke, ọkọ Bimbo Oshin to dólògbé?
- ''Láí! ó dá wa lójú pé kò sí ohun tó jọ ẹ̀dà covid-19 tuntun Omicron Variant ní Naijiria"
- '' Láti Dec 1, ọjọ́ mẹ́rin láàárín ọ̀ṣẹ̀ ní àwọn òṣìṣẹ́ yóò ma a lọ sí ibi iṣẹ́ báyìí ''
- Ẹ̀mí Ọlọ́pàá àti ọ́ọ́físà àjọ ẹ̀ṣọ́ ojú pópó bó níbi idigunjale Banki tó ṣẹ̀ṣẹ̀ wáyé ní Aramoko Ekiti
- Wo Sẹ́nétọ̀ tó fẹ́ gbé bùkátà iléẹ̀kọ́ ìbejì Timithy Adegoke tó kú sílé ìtura ní Ife
- Wọ́n yọ ẹ̀yà ara màmá wa tí wọn pa ní ṣọ́ọ́ṣì Deeper lọ - Ẹbí pariwo
- Ta ni Ola Ibironke, ọkọ Bimbo Oshin to dólògbé?
- 'Oṣù mẹ́sàn-án ni wọ́n fi jí mi gbé tí wọ́n ń fipá bá mi lòpọ̀ títí tó fi di oyún'
Gẹ́gẹ́ bi ó ṣe sọ gbogbo ìgbìyànjú láti dáa padà sáyé ló ja sí pàbó, wọ́n sì gbé lọ sí ilé ìwòsàn níbi tí wọn tí kéde pé ó ti jáde láyé
Nínú alaye gbọọrọ to kọ soju opo Instagram rẹ ni Bimbo Osun tí sọ pe ko burú ju kí ènìyàn pàdánù olólùfẹ́ ẹni lo, ṣùgbọ́n òun dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run.
Bimbo Oshin ni òun ṣe ìdárò ọkọ òun nígbà gbogbo nítorí ó nira àti pé ó sì ń jọ bí àlá náà ni, ṣùgbọ́n òun mọ pe ibikíbi tí ọkọ òun bá wà yóò fẹ ki inú òun máa dùn ni kí ṣeé láti sọ ìrètí nù
Gbajúgbajà òṣèré náà dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo àwọn tó dúró tíì lásìkò tí wá nílé òpó tó fi mọ́ orí adé Olubadan àti àwọn gbajúgbajà Òṣèré gbogbo.

Oríṣun àwòrán, @Dudu
Bakan naa lo dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn egbe òní Gulf Ibadan ni bí ti o ni ọkọ òun jẹ asoju ẹgbẹ́ wọn kì ó tó di ẹni àkọlẹ bo, fún gbogbo nnkan ti wọn ti nígbà tí ọkọ òun wà láàyè àti ìgbà tí ó kú tán.
Bimbo Oshin dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo awon ẹgbẹ́ òṣèré pátá fún ìfẹ́ àti aduro tí. Bákan náà ló dúpẹ́ lọ́wọ́ Oniwo tí ìlú Ìwọ Oba Rasheed Akanbi "A oni fi iru eyi san funrawa loruko Jesu."
Gbajúgbajà òṣèré náà fi kún pé pẹlu bí gbogbo àwọn ènìyàn ṣe ṣe yìí, òun mọ pe inú ọkọ ohun náà fún sí wọn níbikíbi tí ó bá wà













