You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Yoruba World Centre:: Osinbajo àtàwọn àgbà Yorùbá ṣe ìfilọ́lẹ̀ Ibùdó àṣà Yorùbá lágbàyéé
Igbakeji Aarẹ Naijiria, Yemi Osinbajo ti rọ awọn alamojuto ibudo Yoruba l'agbaye, Yoruba World Centre (YWC) lati ṣe agbatẹru bi awọn nkan iṣẹmbaye Yoruba ti awọn kan jigbe tabi ko kuro ni ilẹ Yoruba lọna ti ko ba ofin mu, yoo ṣe jẹ dida pada.
Nibi ayẹyẹ ifilọlẹ Ibudo Aṣa ati nkan abalaye Yoruba, International Centre for Yoruba Arts and Culture (INCEYAC) to waye ni Fasiti Ibadan, ni Osinbajo ti sọ ọrọ naa lọjọ Iṣẹgun.
Osinbajo sọ pe ibudo INCEYAC "gbọdọ darapọ mọ igbesẹ to n lọ ni agbaye lati da awọn nkan iṣẹmbaye naa pada si ilẹ yii.
- Ẹ wo ẹni tó ń jẹ́ Suwebatu nínú ẹbí Baba Suwe àti ohun tó sọ nípa olóògbé
- Bí ètò ìsìnkú Baba Suwe yóò ṣe lọ rèé, bó ṣe ń wọ ilẹ̀ sùn lónìí
- "Lẹ́yìn ti mo lo ọdún 42 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, wọ́n tú mi sílẹ̀ pé ń kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn"
- Bàbá mi máa ń sunkún torí bí kò ṣe le padà ṣeré tíátà mọ́ - Ọmọ Baba Suwe
- Clem Ohameze, òṣèré tíátà ní àìlera, ó ń bẹ̀bẹ̀ àdúrà lórí iṣẹ́ abẹ
- N kò rán ẹnikẹ́ni láti pín ìrẹ̀sì àti ẹ̀wà tórí ìbò ààrẹ 2023 - Bola Tinubu figbe ta
- Ẹ màá múra sílẹ̀ láti ra lítà epo kan ní ₦320 sí ₦340 lọ́dún 2022- NNPC
- Tówẹ́ẹ̀lì ni bàbá mi ró mọ́ ìdí nígbà tí àwọn sọ́jà wọlé mu lọ - Ọmọ Akintunde
- Jàndùkú kọlù mi, gé mi lára bíi olè torí mo jẹ́rìí tako ìjọba níbi ìwádìí ìpànìyàn Endsars Lekki''
- Femi Fani-Kayode ṣàlàyé bí ìrìnàjò rẹ̀ sọ́dọ̀ EFCC ṣe jẹ́
- Ẹ lọ san ₦20bn owó ìtanràn fún Sunday Igboho títí January - Iléejọ́ fọnmú fún DSS
Koda, ibudo yii le jẹ ibi isinmi fun awọn nkan iṣẹmbaye ti wọn ba da pada, amọ ti ibi ti wọn ti gbe e ko ba tete jẹ mimọ,"
Ẹni to ṣe agbatẹru ibudo tuntun naa, Alao Adedayo sọ pe ọdun 2014 ni oun ti bẹrẹ iṣẹ lori rẹ, pẹlu erongba lati da ibudo kan silẹ nibi ti awọn onimọ le lọ lati ṣe iwadii nipa ìtàn, àṣà ati awọn nkan iṣẹ ọna nilẹ Yoruba.
Lara awọn to peju sibi ayẹyẹ naa ni Alaafin ilu Oyo, Oba Lamidi Adeyemi, Gomina ipinlẹ Ooy, Ogun ati Osun, botilẹ jẹ pe awọn igbakeji wọn lo ṣoju wọn.
Wọn si rọ awọn alakoso ibudo naa pe ki wọn o ma a jẹ abuku ba akọsilẹ itan tabi ki ọrọ oṣelu bọ iṣẹ wọn.
Bakan naa ni Aarẹ Ọna Kakanfo ilẹ Yoruba, Iba Gani Adams naa wa nibẹ.