BBC Igbo Townhall meeting: Kìí ṣe jàgídíjàgan ni ọ̀nà àbáyọ sí ìṣòro Naijiria - Ohaneze, Mefor, Briggs

Awọn onimọ kan to jẹ ẹya Igbo ni Naijiria ti sọ pe iwa jagidijagan kọ ni ọna abayọ si iṣoro ti Naijiria n koju lọwọ yii.
Awọn eeyan naa lo sọ ọrọ ọhun lasiko ifọwerọ kan ti BBC ṣe onigbọwọ rẹ.
Lara awọn to wa nibi ifọrọwerọ naa ni Alex Ogbonna lati ẹgbẹ Ohaneze, Mazi Ogbonnaya ati Annkio Briggs.
- Iléesẹ́ Twitter ti ń bá ìjọba Nàìjíríà sọ̀rọ̀ papọ̀- Alhaji Lai Mohammed
- Àjọ EFCC mú àwọn afurasí aàdọ́ta tó ń lu jìbìtì lórí ayélujára ní Ibadan
- Orílẹ̀-ède 174 káàkiri àgbáyé ní ìwọ́de Yoruba Nation yóò tí wáyé ní June 12- Ẹgbẹ́ Yoruba One Voice
- Ìbínú ńlá ti mú Àǹjọ̀nú tó ń jẹ́ Emmanuel lọ....àwọn kan ń sọ̀fọ̀ Lucifa tó lọ- Okotie
- Ẹ̀yin olóṣèlú, ẹ má fi ìṣẹ̀lẹ̀ ìpànìyàn Igangan dá ìjà ẹlẹ́yàmẹ̀yà sílẹ̀- YWG
Briggs sọ pe oun ti gbọn lasiko ogun abẹle Biafra, iriri ogun naa kii ṣe iriri ti oun fẹ lati ri lẹẹkan sii.
O ni "Mo ranti daadaa pe asiko ogun abẹle, awọn ohun to ṣẹlẹ ṣaaju ogun naa lo tun n ṣẹlẹ bayii laye ode oni."

Oríṣun àwòrán, Other
Briggs ṣalaye pe awọn ohun to n ṣẹlẹ nilẹ Igbo lọwọ awọn eeyan lati ilẹ okeere ninu, awọn eeyan naa si n gbimọ lati da omi alaafia agbegbe naa ru ni.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, inu awọn eeyan ilẹ Igbo ko dun si ohun to n lọ lọwọ ni Naijiria bayii.
Sugbọn ni ṣe lo yẹ ki gbogbo ipinlẹ to wa nilẹ Igbo ṣe ara wọn ni oṣuṣu ọwọ ju ki wọn maa da wahala silẹ lọ.
O pari ọrọ rẹ pe, kii ṣe Naijiria nikan ni awọn eeyan ti n binu si ijọba.
Amọ̀, tilẹ jẹ pe o jọ bi ẹni pe ijọba Naijiria ko naani awọn ẹya Igbo, rukerudo kọ ni ọna abayọ.

Oríṣun àwòrán, Other
Ẹwẹ, nigba to n da si ọrọ naa, Alex Ogbonna sọ pe irufẹ ọrọ odi ti awọn eeyan n sọ lo tubọ n da kun wahala to wa nilẹ tẹlẹ.
O ni gẹgẹ bii iriri ti oun ti ri, ipade apero ni ọna to dara ju lati yanju aawọ ju rogbodiyan lọ.
Bo tilẹ jẹ pe o ni inu oun dun si agbekalẹ ikọ alaabo Ebube Agu ti awọn gomina iha naa ṣagbekalẹ rẹ, o ni ikọ naa ni lati ṣiṣẹ wọn bii iṣẹ lati daabo bo awọn eeyan agbegbe wọn.

Oríṣun àwòrán, Annkio Briggs
Ni ti Mazi Ogbonnaya, o sọ pe o yẹ ki awọn eeyan ẹya Igbo gbagbe ohun to ti ṣẹlẹ sẹyin, ṣugbọn ki wọn maa wo ọjọ iwaju.

O ni o yẹ ki awọn ọdọ lọ yẹ iwe itan wo, ki wọn mọ ohun to ti ṣẹlẹ sẹyin ki wọn to maa ṣe awọn ohun ti wọn n ṣe.
O pari ọrọ rẹ pe ki awọn ọdọ dẹkun ati maa ba awọn adari ja ṣugbọn ki wọn wo bi wọn ṣe le kin wọn lẹyin ki wọn le ṣe aṣeyọri.
- Àwọn tí a jọ ń se ìjọba ní Nàìjíríà sisẹ́ gba ipò wọn lábẹ́ ìjọba mi ni- Aarẹ Buhari
- Ẹyìn ọ̀dọ́ Nàìjíríà, tẹ́ bá ríṣẹ́ ṣe, ọwọ́ ara yín lẹ fi ṣe ara yín - Buhari
- Àjọ EFCC mú àwọn afurasí aàdọ́ta tó ń lu jìbìtì lórí ayélujára ní Ibadan
- Ọwọ́ tẹ bàbá ẹni ọdun 60 níbi tó ti n bá ọmọ ọdún mẹ́sàn-án lòpọ̀
- Iléesẹ́ Twitter ti ń bá ìjọba Nàìjíríà sọ̀rọ̀ papọ̀- Alhaji Lai Mohammed














