Ayo Adebanjo: Màá túbọ̀ parí aáwọ̀ Obasanjo àti Gani Adams torí ilẹ̀ Yorùbá kò gbọdọ̀ bàjẹ́

Oríṣun àwòrán, Etim Baba Grace Okon/Facebook
Eekan inu ẹgbẹ Afenifere, Alagba Ayo Adebanjo ti fi aidunnu rẹ han lori aawọ to wa laarin aarẹ ana, Oloye Olusegun Obasanjo ati Aarẹ Ọna Kakanfo fun ilẹ Yoruba, Oloye Gani Adams.
Laipẹ yii ni Oloye Adebanjo pẹtu si ija to wa laarin awọn mejeeji nile rẹ ti Obasanjo ati Adams si sọ ohun to n dun wọn nibi ipade ọhun.
Adebanjo ni "Obasanjo fún ra rẹ lo mu ọjọ toun ati Gani yoo wa lati wa pari aawọ to wa laarin wọn, awọn mejeeji si wa lati yanju ọrọ naa"
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọ̀pọ̀ nkan tó n ṣẹlẹ̀ kò jẹ́ kí n gbàgbọ́ pé Naijiria wà ní abẹ́ ìdarí ẹnikẹ́ni - Wole Soyinka
- Ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ṣoro ní Ijebu Ode, ọ̀pọ̀ ẹ̀mí sọnù
- Àlàyé rèé lórí ìdí tí mo fi lọ sílé Tinubu - Rashidi Ladoja
- ‘Sim Card’ títà àti ìforúkọsílẹ̀ rẹ̀ dèèwọ̀ ní Nàíjíríà - NCC
- Ààrẹ Akufo-Addo la Mahama mọ́lẹ̀ wọlé ìbò ààrẹ Ghana fún sáà kejì
- Ẹ̀yin tí ẹ máa ń bú àwon tó sanra ni ẹ ń jẹ́ kí wọ́n ronú pa ara wọn - Eniola Badmus
- Ṣé lóòtọ́ ni tírélà ti gba ààrín Ronke Odusanya àti bàbá ọmọ rẹ̀, Jago? Nkan tí a mọ̀ nìyíì
- Mo ti kúrò ní ààfin Oyo, kí ìròyìn tó ò jáde pé èmi àti Wasiu Ayinde n fẹ́ ara wa - Olori Badirat
"Ṣugbọn inu mi ko dun rara lẹyin ti mo gbọ pe wọn tun ti n tahun si ara wọn, paapaa julọ Obasanjo," Adebanjo lo sọ bẹẹ.

Oríṣun àwòrán, Ayo Ademokoya/Facebook
Eekan Afenifere fikun ọrọ pe, Obasanjo tun ṣe awada pẹlu Gani pe o gbọdọ fún oun lowo oye to jẹ lẹyin ti oun yanju ọrọ naa tan.
Pa Adebanjo ni 'emi lawọn mejeeji tẹ papaa julọ Obasanjo pẹlu bi wọn ṣe tun n sọrọ si ara wọn."
"Ohun ti mo n ṣe ni pe ki ilẹ Yoruba maa bajẹ, amọ a n jekuru ko tan lawo, wọn tun gbọn ọwọ sabọ ni ọrọ yii o," baba Adebanjo lo wí bẹẹ.
Eekan Afenifere naa sọ pe ti ina ko ba tan laṣọ, ẹjẹ kii tan leekanna, o ni oun ṣetan lati pe awọn mejeeji pada lati yanju ọrọ naa.
Adebanjo ni oun yoo sa gbogbo agbara oun lati wa ojutu si aawọ naa nitori "ilẹ Yoruba ko gbọdọ bajẹ."
















