Bashorun High School Ibadan: Ṣé lóòtọ́ ni ajínigbé sọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ méjí di iṣu ní Ibadan?

Oríṣun àwòrán, Others
Ijọba ipinlẹ Ọyọ ti fesi si iroyin to n ja ranyin nilẹ pe ajinigbe kan ti ọwọ tẹ sọ akẹkọọ meji ni ileẹkọ Bashorun High School, Ibadan di isu.
Kọmiṣọnna eto ẹkọ nipinlẹ Oyo, Rahman Abdul-Raheem ni ko si otitọ kankan ninu iroyin naa lasiko to n ba awọn akẹkọọ, obi ati awọn ojulumọ sọrọ ni ileẹkọ naa.
Raheem lo ṣe abẹwo si ileẹkọ naa lati ṣewadii iṣẹlẹ naa ti ohun ja ranyin lori ẹrọ ayelujara.
- Bí mo ṣe dáná sun àlè ọkọ mi tí mo tún fẹ́ sá lọ nípinlẹ̀ Ogun - Ìyàwó ilé
- Ibi tí ọ̀rọ̀ dé dúró rèé lórí ikú akẹ́kọ̀ọ́ Sylvester Oromoni tí wọ́n ní àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn ní Dowen College lù pa
- Ìjọba Ìpínlẹ̀ Ondo sọ̀rọ̀ lórí ìdájọ́ tó dá Sotitobire láre pé kò jí ọmọ kankan gbé
- Akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún ló wọlé lu ọmọ mí tó fi kú, kìí ṣe bọ́ọ̀lù ló gbá - Baba akẹ́kòó Dowen fèsì
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá kéde ìgbaniṣíṣẹ́ fáwọn àkàndá ẹ̀dá
- Àwọn ọ̀dọ́ Eruwa ṣe ìwọ́de lórí ikú Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura ní Ife
Iroyin to n ja ranyin naa ni ajinigbe lo sọ awọn akẹkọọ meji da isu pẹlu ''pampers'' ti wọn ko tii lo.
Iroyin ọhun fikun un pe awọn ẹṣọ alaabo labẹle ni wọn fi panpẹ mu ajinigbe naa ni agbegbe Bode Wasinmi-Bashorun, ti ko jina si ileẹkọ naa.
Eleyii da ipaya silẹ fun awọn eniyan ni agbegbe naa paapaa awọn obi ti wọn fi ọmọ si ileewe ọhun.
Amọ kọmiṣọnna fun eto ẹkọ nipinlẹ naa ni iwadii awọn pẹlu awọn alaṣẹ ileewe naa fihan pe ko si akẹkọọ kankan to di awati ni ileewe naa.
Bakan naa ni kọmiṣọnna pe fun alaafia ati ki awọn eniyan fi ọkan balẹ.
O ni ẹṣọ alaabo naa ti bẹrẹ iwadii pẹrẹwu lori iṣẹlẹ naa lati fi idi iṣẹlẹ to waye gan an lede fun awọn eniyan.
Kọmiṣọnna fun eto ẹkọ naa fi da awọn araalu loju pe eto aabo awọn araalu jẹwọn logun, ti igbiyanju si n lọ lati ri pe aabo to daju wa fun awọn araalu.













