You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Lagos Yoruba Nation rally: Ìjọba Eko jáwọ́ nínú ẹ̀sùn ìpànìyàn tó fi kan Ọba Ogboni
Ijọba ipinlẹ Eko ti jawọ kuro ninu ẹjọ ẹsun ipaniyan to fi kan ẹnikan lara awọn oluwọde Yoruba Nation, Tajudeen Bakare, to jẹ Olori ẹgbẹ Ogboni.
Ọjọ kẹta, oṣu Keje, ni awọn agbofinro mu Ọgbẹni Bakare pẹlu awọn oluwọde bi mẹtadinlaadọta lasiko ti wọn n ṣe iwọde ni Ojota, nipinlẹ Eko.
Lọjọ gan-an ni ibọn pa ọdọmọbinrin kan, Jumoke Oyeleke,nitosi ibi ti iwọde naa ti waye, ti ileeṣẹ ọlọpaa si sọ lasiko naa pe ibọn awọn kọ lo pa ọmọbinrin naa.
Lẹyin ọjọ diẹ ti Jumoke ku, ni ijọba ipinlẹ Eko ati ileeṣẹ ọlọpaa kede pe ẹnikan lara awọn oluwọde ti ọwọ tẹ (Ọgbẹni Bakare), ni iwadii fihan pe o pa ọmọbinrin naa.
- Ọ̀rẹ́bìnrin kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó gún "Sugar daddy" rẹ̀ pa
- Ààrẹ Ògbóni sọ òkò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí Gani Adams torí bó ṣe tàbùkù Ọba Ogboni tó ṣe ìwọ́de Yorùbá Nation
- Ilé ẹjọ Májísírèètì Yaba nípinlẹ Eko ti gba béèlì àwọn olùwọde Yoruba Nations 49 tí wọn wa ní àhámọ
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó yóò ṣe ìwádìí òhun tó ṣ'okùnfà ikú Jumoke tí ọtá ìbọn bá ní Ojota
- "Á dá ohun àlùmọ́ọ́nì wa jọ láti gbèjà Sunday Igboho nílé ẹjọ́"
- Wo àwọn ìgbésẹ̀ tí Sunday Igboho gbé, tó fi di ọ̀tá ìjọba
- Ẹran Akíka(Pangolin) àti ìwo Erin d'ẹ́rù b'olẹ̀, ìjọba f'òfin gba bílíọ́nù 22 ẹran ara wọn
Eyi to mu ko ṣi wa ni ahamọ awọn ọlọpaa botilẹ jẹ pe wọn ti gba beeli awọn ti wọn jọ ko wọn pọ nibi iwọde.
Ṣugbọn ni bayii, iroyin sọ pe wọn ti tu Ọgbẹni Bakare silẹ ni ahamọ agbofinro.
Ninu atẹjade to fi sita, eyi to tẹ BBC Yoruba lọwọ, agbẹnusọ fun ẹgbẹ Ilana Omo Oodua, to jẹ ẹgbẹ to n ṣagbatẹru awọn iwọde Yoruba Nation, Maxwell Adeleye sọ pe wọn ti tu Ọba Ogboni silẹ.
O ni ijọba ipinlẹ Eko ti sọ pe oun jawọ lori ẹsun ipaniyan ti oun fi kan Ọgbẹni Tajudeen Bakare, Ọba Ogboni.
Bakan naa lo sọ pe wọn ti fi silẹ ko kuro ni ahamọ.
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Ìjọba Amẹ́ríkà ti kó abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 mílíọ̀nù mẹ́rin fún Nàìjíríà
- Irọ́ ní ò, Adeyinka Daniel, akẹ́kọ̀ọ́ FUTA tí kú kí wọ́n tó gbé e wá sí ''health Centre'' FUTA
- Àlááfíà ni Bola Tinubu wà - Sanwo - Olu
- Olórí ọ̀dọ́ ẹgbẹ́ PDP sọ àbùkù ọ̀rọ̀ sí Ààrẹ Buhari àti SGF, ẹ̀wọ̀n jàntò ló rí he!