You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Igboho, Yoruba Nation rally: A kò gbọ́ pé Sunday Igboho fẹ́ ṣe ìwọ́de ní ìpínlẹ̀ Eko- Kọmisọ́nnà ọlọ́pàá`
Gbajugbaja ajijagbara nilẹ Yoruba, Ọgbẹni Sunday Adeyemo, ti ọpọ eeyan mọ si Sunday Igboho kede pe oun yoo ṣe iwọde idasilẹ orilẹ-ede Oduduwa ni ipinlẹ Eko, lọjọ kẹta, oṣe Keje.
Amọ ileeṣẹ ọlọpaa ti sọ pe ko si ẹni to fi ọrọ iwọde naa to awọn leti.
Kọmisọnna ọlọpaa nipinlẹ naa, Hakeem Odumosu sọ fun iwe iroyin 'The Nation' pe oun ko gbọ pe iwọde kankan fẹ ẹ waye nipinlẹ Eko, nitori pe ẹnikẹni ko kọ iwe si ileeṣẹ ọlọpaa lati sọ fun wọn.
"Ti asiko ba to, ao mọ nkan ti ao ṣe nipa rẹ."
- Wo àwọn nkán tó ṣẹlẹ̀ níbi ìwọ́de Yoruba Nation tó ti wáyé sẹ́yìn
- Àwọn olùwọ̀de Yoruba Nation mú afurasí òṣìṣẹ́ DSS níbi ìwọ́de l‘Osogbo
- Obìnrin bíi 1000 láti orílẹ̀èdè 37 bẹ Ọọ̀ni wò fún ìdásílẹ̀ orílẹ̀èdè Oduduwa
- Ẹ̀rú Fulani ni Aregbesola, ara sì ló ń ta á torí àṣeyọrí ìjìjàgbara Yoruba nation - Ilana Omo Oodua
- Pé mo gba ìwọ́de lááyè kò túmọ̀ sí pé mo faramọ́ Oduduwa Nation - Akeredolu
Ṣaaju ni gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti kede pe ipinlẹ naa ko lọwọ si ipolongo pe ki ẹya Yoruba pin kuro ni ara orilẹ-ede Naijiria.
Ninu ikede to fi sita ni ọjọ diẹ sẹyin, gbagede Freedom Park ti wọn fi sọri agba agbẹjọro, Oloogbe Gani Fawẹhinmi, eyi to wa ni agbegbe Ọjọta nipinlẹ Eko, ni Sunday Igboho sọ pe iwọde Yoruba Nation naa yoo ti waye.
Igboho ni "ko si ẹnikẹni to le sọ pe ki a ma wa si ipinlẹ Eko, nitori pe iwọde alaafia ni a fẹ sẹ. A ti ṣe ni Ogun, Ondo, Ekiti ati Osun.
Ati pe ere gbogbo di Freedom Park.
- Ẹ ṣeun, ẹ kú àdúrótì mi! Ẹ wo ọ̀rọ̀ tí Tope Alabi padà sọ nípa awuyewuye tó wáyé lóri orin Oniduro Mi
- Ọwọ́ tẹ ọmọdébìnrín tó jí ara rẹ̀ gbẹ́ nítorí ìyá rẹ̀ ní kó lọ kọ́ ẹ̀kọ́ láti ṣe dókítà
- Dino Melaye fi ọkọ Rolls Royce bùgá lórí Instagram, ni oníṣòwò ọkọ́ bá ní kó wá san gbèsè owó ọkọ̀ tó jẹ́ òun
- Ẹ wo ohun tí a mọ̀ nípa bí agbébọn ṣe gbẹ̀mí sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀, Titus Badejo Ejanla ní ìlú Ibadan
- Àjọ JAMB ṣèlérí ìdánwò mìí fún àwọn tí NIN jákulẹ̀, ó tún fòfin de ibùdó CBT 25
- Ẹ wo bí olówó 'billionaire', Usifo Ataga ṣe kú ikú òjijì ní Eko
- Ṣé lóòtọ́ ni àwọn ọmọ ogun òfurufú Nàìjíríà ṣèèṣì pa máàlú 1,000 ní Nasarawa?