Iṣẹ́ ìdọ̀tí ni mò ń ṣe àmọ́ ó ń san owó iléèwé ọmọ - Akẹ́kọ̀ọ́gboyè Kehinde Adeoye
“Ọja taa n ta, ti a o ko lọ si ibi kankan ti awọn eeyan si n wa si ile lati wa koo, Ọlọrun lo ṣee.”
Kehinde Adeoye jẹ ẹni to wa lati iran awọn amọkoko Abeokuta ni ipinlẹ Ogun. Ninu ifọrọwanilẹnuwo yii pẹlu BBC Yoruba, Kehinde ṣalaye bi o ṣe gbọnju ba koko ṣiṣe ninu ẹbi rẹ.



Bakan naa lo jẹ ko di mimọ pe lẹyin ti oun tilẹ kawe gboye tan nile ẹkọ awọn olukọni, ti o wa iṣẹ titi titi ti ko ri, o pinu lati pada sile sidi owo ẹbi rẹ eyi tii ṣe koko mimọ.
“Mi o ronu pe mo tilẹ wa iṣẹ ijọba mọ. A n gba awọn eeyan si iṣẹ, o si n to waa jẹ, mi o tilẹ ronu iṣẹ ọba mọ.
Iṣẹ taa ba nile nidile iya ati nidile baba ni koko mimọ, kii ṣe eyi ti a kọ.












