Ẹni ọdún 27 tó ṣá bàbá rẹ̀ pa l'Ogun dèrò àtìmalé

Oríṣun àwòrán, Abimbola Oyeyemi
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ ogun ti fi ṣikun ofin mu okunrin ẹni ọdun mẹtadinlọgbọn kan, Sikiru Ibrahim, lori ẹsun pe o ṣa baba rẹ pa.
Wọn mu afurasi naa ni ọgbọn ọjọ, oṣu Kẹta, ọdun 2022, lẹyin ti ọgbẹni kan, Abiodun Sunday, fi ọrọ rẹ sun ni ago ọlọpaa Onipanu.
Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ ileeṣẹ naa, Abimbola Oyeyemi fi ṣọwọ si BBC lo ti fi ọrọ naa lede.
- Wo àsọtẹ́lẹ̀ tí Dejo Tunfulu tí sọ ṣáájú nípa irú iku tó lè pa
- Wèrè ọlọ́mọ ní Dejo Tunfulu, ọmọ mẹ́rin ní ìyá wa dà sílẹ̀ fún, tó sì bá ọkọ míì lọ - Ọmọ olóògbé
- Àrá sán pa ọ̀dọ́kùnrin mẹ́rin tó ń gbá bọ́ọ̀lù l'Ondo
- Ramadan wọlé dé! Wo nkan márùn-ún tó yẹ kó mọ̀ nípa oṣù ọlọ́rẹ
- Wo gbajúmọ̀ aláwàdà Yorùbá méjọ tó ti kú saájú Dejo Tunfulu
- Àtẹ̀jíṣẹ́ kan tó wọ orí fóònu mi, ló fi òpin sí ìbànújẹ́ mi lórí ikú Dare ọmọ mi - Adeboye
- Baba Ijesha ń fẹ́ Princess, ìyá Princess gan sọ lójú mi pé kó tọ́jú ọmọ òun dáadáa - Ẹlẹ́rìí Kẹrin
- Àwọn aṣòfin ń dúnkookò láti yanṣẹ́ lódì títí tíjọba yóò fi pèsè ààbò tó péye
Oyeyemi sọ pe oloogbe ọhun, Mumuni Ibrahim, to jẹ ọlọdẹ oru de lati ibi iṣẹ rẹ, to si ba afurasi naa to n sun.
Lẹyin naa lo bere lọwọ afurasi ọhun to fi n sun ni irufẹ akoko bẹẹ.
Ka to wi, ka to fọ, o ti fa ada yọ, to si ṣa baba rẹ ni igba marun un ọtọtọ.
Ni kete ti iṣẹlẹ naa to awọn ọlọpaa leti ni wọn tẹkọ leti lọ si ibi ti iṣẹlẹ ọhun ti waye ti wọn si fi ṣikun ofin mu afurasi naa, nigba ti wọn gbe baba rẹ digbadigba lọ sile iwosan fun itọju.
Atẹjade naa ni "Afurasi naa, ti igbagbọ wa pe o jẹ ọmọ ẹgbẹ okunkun ko le ṣalaye eredi to ṣe ṣa baba rẹ pa nigba ti a fi ọrọ wa lẹnu wo."
"Nigba to di ọjọ kọkanlelọgbọn, oṣu Kẹta, ọdun 2022 yii ni oloogbe naa jade laye lasiko to n gba itọju lọwọ, ti awọn mọlẹbi rẹ si sọ pe awọn gbọdọ sin oku rẹ ni ilana ẹsin rẹ."
Ẹwẹ, kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Ogun, Lanre Bankole ti paṣẹ ki wọn gbe afurasi naa lọ si ẹka ti wọn ti n ṣe iwadii ẹsun ipaniyan ni ẹka CID fun iwadii ni kikun, ko si tun le tete foju bale ẹjọ.














