Omoyeni rí ẹ̀wọ̀n he fẹ́sùn fífi abẹ ya ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lára

olopaa

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Yorùbá bọ̀ wọ́n ní fúnra ra oníkọ́ ní ń fi ẹnu ara rẹ̀ pé ikú, bí ènìyàn bá sì ní ìkà méjì yóò fi ọ̀kan ṣe ara rẹ̀.

Ilé Májísíréètì kan nílùú Akure, ìpínlẹ̀ Ondo ti fi obìnrin kan Omoyeni Opeyemi sí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́ta àti àbọ̀ fẹ̀sún pè ó fi ìyà tí kò tọ́ jẹ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, Joel Sunday.

Ní nǹkan bí ọ̀sẹ̀ méjì sẹ́yìn ni àjọ ọlọ́pàá nawọ́ gán Omoyeni Opeyemi nígbà tí fọ́nrán kan tó ṣàfihàn bó ṣe fi abẹ yá Joel Sunday, ọmọ ọdún méjìlá, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lára, ṣe gba orí ẹ̀rọ ayélujára kan.

Kini o sele nibe ki Adajo to da ẹjọ́ rẹ̀?

Nínú fọ́nrán náà, Joel ni àpá tútù wà ní ara rẹ̀, tí ẹ̀jẹ̀ bòó, tí kò sì le rìn dáadáa.

Àkọlé fídíò, Ọdún mẹ́ẹ̀dógún sẹ́yìn ni ojú bẹ̀rẹ̀ sí ní dùn mí tí àwọn dókìtà sì ní Glaucoma ló fàá

Opeyemi, ẹni ọdún mẹ́rìndínlógójì tó tún jẹ́ opó, ni wọ́n ka ẹ̀sùn márùn-ún sí lọ́rún tó fi mọ́ ìfọmọṣerú, ìgbèrò àtipànìyàn, àti ẹ̀sùn mẹ́ta mìíràn.

Adájọ́ O. A. Edwin nígbà tó ń gbé ìdájọ́ rẹ̀ kálẹ̀ ní Opeyemi jẹ̀bi ẹ̀sùn mẹ́rin nínú márùn ún tí wọ́n fi kàn án.

Àkọlé fídíò, Khadijat Okunnu:Olùdíje ipò ààrẹ Nàìjíríà tó sọ pé nkán gbódọ̀ dàrú ní Nàìjíríà kò