Àwọn agbébọn yabo ibi ètò ìgbéyàwó, jí ìyàwó àti àwọn ènìyàn mẹ́jọ mìíràn gbé lọ

Oríṣun àwòrán, others
Bí ènìyàn bá ti dá ọjọ́ ìnàwó sọ́nà ní ọkàn rẹ̀ yóò ti ga tí yóò sì máa gbàdúrà kí ọjọ́ kò láyọ̀. ki àwọn agbébọn ma ba a ni alejo.
Ọ̀rọ̀ kò fẹ́ rí bẹ́ẹ̀ fún ìyàwó tuntun yìí bí àwọn agbébọn tí iye wọn fẹ́ẹ̀ tó ọgọ́rùn-ún ṣe ya wọ àwọn ìlú kan ní ìjọba ìbílẹ̀ Lavun, ìpínlẹ̀ Niger.
Àwọn agbébọn náà ni ìròyìn ní wọn yabo ibi ìgbéyàwó náà tí wọ́n sì jí ìyàwó gbé lọ.
Bákan náà ni wọ́n pa ènìyàn mẹ́jọ, tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì farapa níbi ìkọlù náà.
Lára àwọn ìlú tí wọ́n ṣe ìkọlù sí ni Egbako, Ndaruka, Ebbo, Ndagbegi, Tshogi, Gogata àti Ndakogitu.
Ní alẹ́ ọjọ́ Àbámẹ́ta ní ìkọlù náà bẹ̀rẹ̀ títí di àárọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ Àìkú.
- Kí ló wáyé níbi ìpàdé NANS àti ìjọba àpapọ̀? àlàyé rèé
- Victor Akinwa tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé o gún orí bàbá rẹ̀ nínú odó ti kó sí gbaga ọ́lọ́pàá ní Ondo
- Wo àwòràn ohun tó sẹlẹ̀ ní UKraine
- Ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ yóò bẹ̀rẹ̀ ìwọ́de tako ìyanṣẹ́lódì ASUU lónìí
- Belarus ní ààyè ìpàdé ìpẹ̀tùsááwọ̀ láàrín Ukraine àti Russia ti wà níkàlẹ̀
- Ta ni Ajé tí àwọn ọmọ Yorùbá lágbáyé ń ṣọdún rẹ̀ ní Ile Ife lónìí?
- Ìjọba Nàìjíríà gbọ́dọ̀ tọrọ àforíjìn lọ́wọ́ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu àti gbogbo àjìjàngbara tí wọ́n fìyà jẹ- Sowore
- Olùkọ́ dèrò àgọ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn tó na akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́sàn án lálubami
Kí ni àwọn agbébọn náà ṣe?
Ní ìlú Gbacitagi, àwọn agbébọn náà yabo ibi igbéyàwó, jí ìyàwó, ọmọdébìnrin kan, owó àti àwọn ohun èlò mìíràn gbé lọ.
Bákan náà ni ìròyìn ní wọn pa ènìyàn kọ̀ọ̀kan ní Ebbo, Tsonfadagabi, Tsoga àti Kanko tí wọ́n sì ba àwọn ọkọ̀ jẹ́.
Kọmísọ́nà fétò ìjọba ìbílẹ̀ ìpínlẹ̀ Niger Emmanuel Umar fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀.
Kí ni àwọn ara ìlú ṣe fún àwọn agbébọn náà?
Àwọn fijilanté gbìyànjú láti kojú àwọn agbébọn náà léyìí tó fà á kí wọ́n dojú ìbọn ko ara wọn.
Fijilanté méjì àti àwọn ara ìlú mẹ́rin ló bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ















