Àwọn ọba Yorùbá l'órílẹ̀èdè Benin Republic ṣe ìpàdé, ohun tí wọ́n fẹnukò láti ṣe lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho nìyí

Awọn ọbalaye lẹyin ipade wọn ni ilu Adjohoun

Awọn ọbaalye iran Yoruba lorilẹede Benin Republic ti ipade laafin aladjohoun tilu Adjohoun ni Benin lọjọ Aiku.

Ohun ti ipade wọn naa da le lori ni ọrọ Sunday Adeyẹmọ ti ọpọ mọ si Sunday Igboho.

Lọjọ aje ni oloye Sunday Igboho yoo pada foju ba ile ẹjọ lorilẹede Benin Republic lati mọ boya wọn yoo tuu silẹ ni tabi ki wọn daa pada sorilẹede Naijiria gẹgẹ bi awọn alaṣẹ ijọba.

Lẹyin ipade naa eyi to pari ni nnkan bi agogo meji ọsan orilẹede Naijiria, awọn ọbalaye naa ṣe lalaye fun ikọ BBC News Yoruba to wa nibi ipade naa pe ipade naa wa lati mọ ọna abayọ ati igbesẹ ti awọn yoo gbe lori ọrọ naa ni. Wọn ni ohun ti awọn fi ẹnu ko le lori ni lati kọ iwe si aarẹ orilẹede Benin pẹlu minisita feto idajọ, minisita fọrọ abẹle ati olori ileegbimọ aṣofin apapọ lorilẹede naa.

Gẹgẹ bi ohun ti wọn sọ, lẹyin ti wọn ba gbe gbogbo igbesẹ wọnyii ni wọn yoo to lanfani ati ba awọn oniroyin sọrọ.

Awọn lọbalọba naa ko ṣalaye fun BBC News Yoruba ohun ti wọn fẹ kọ sinu iwe ti wọn fẹ kọ naa nitori pe gẹgẹ bi wọn ṣe sọ, titu aṣiri ohun ti wọn fẹ fi ranṣẹ si awọn eekan ijọba orilẹede naa lee pagidina ohun ti wọn fẹ gan an.

Ọba Siyan aladjohoun tilu Adjohoun ṣalaye pe awọn ọbalaye naa pẹlu yoo gbiyanju ati ṣe abẹwo sile ijọba orilẹede naa ni ọjọ Aje bi esi iwe awọn naa ko ba tete jade.