Niger school kidnap: Àwọn jàndùkù ajínigbé mú bábá tó gbé owó ìtúsílẹ̀ lọ fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n jígbé mọ́lẹ̀

Awọn aga ilẹ ẹko

Oríṣun àwòrán, Reuters

Eemọ lukutu pẹbẹ, awọn janduku ajinigbe ti mu ẹni to gbowo itusilẹ fawọn ọgọrun akẹkọọ ileewe Salihu Tanko Islamic Secondary School niluu Tegina nipinlẹ Niger mọlẹ.

Iroyin sọ pe awọn janduku ọhun ni owo itusilẹ ti ko wa ko pe lo jẹ ki awọn mu un mọlẹ.

Akọroyin BBC, Ishaq Khalid ṣalaye pe awọn obi awọn akẹkọọ naa ti da ẹgbẹẹgbẹrun owo dọla fun itusilẹ awọn akẹkọọ ọhun.

Àkọlé fídíò, Japan: Ẹ wo arákúnrín tó ń ta ilé àwọn òkú fún àwọn tó ní ìfẹ́ sí

O ti to bi oṣu meji bayii tawọn ajinigbe ti gbe awọn akẹkọọbinrin ati akẹkọọbinrin sa lọ nipinlẹ Niger.

Ọga ile ẹkọ naa sọ pe o yẹ kawọn ajinigbe le tu awọn akẹkọọ naa silẹ lẹyin ti wọn ti gba ẹgbẹrun marunlelaadọrin owo dọla tii ṣe ọgbọn miliọnu naira.

Ṣugbọn o ni ọrọ ti polukuru musu bayii lẹyin ti wọn mu baba to gbowo lọ fun wọn mọlẹ.

Iru nkan bayii ko wọ pọ pẹlu awọn ajinigbe lorilẹede Naijiria.

O ti le ni ẹgbẹrun kan akẹkọọ tawọn ajinigbe ti ji lọ lawọn ile ẹkọ girama ni Naijiria lati oṣu kejila ọdun 2020 di akoko yii.

Ọpọlọpọ wọn lo si wa ni akata awọn ajinigbe pawo yii titi di asiko yii.