Kemisola Ogunniyi: Ọmọ tó bí sọ́gbà ẹ̀wọ̀n ló kọ̀kọ́ gba ẹ̀bùn ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́, kí ti ìyá rẹ̀ tó dé

Kemisola Ogunniyi

Lati igba to ti gba itusilẹ nile ẹjọ, se ni idunnu ohun ayọ kan n ṣubu lù ara wọn fún Kemisola Ogunniyi.

Kemisola jẹ akẹkọọ ọmọ ọdun mejidinlogun ti ijọba sọ si ẹwọn pe o kopa ninu iwọde Endsars ni ipinlẹ Ondo.

Eyi taa tun ri gbọ laipẹ yii ni pe obinrin iya ikoko naa ti ri eto ẹkọ ọfẹ gba lọdọ ẹlẹyinju aanu kan.

Agbẹjọro rẹ, Tope Temokun lo fidi ọrọ yi múlẹ fun BBC Yoruba.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni ẹni tó ta Kemisola lọọrẹ yii jẹ alaanu, orukọ rẹ si ni Bamidele Omosehin, tii se oludasilẹ Bamidele Omosehin Foundation to sì jẹ ọmọ ipinlẹ Ondo.

Temokun salaye pe bayii, anfaani ẹkọ ọfẹ yii kan sisan owo idanwo Neco ati Idanwo igbaniwọle si yunifasiti ati owó ẹkọ rẹ titi ti yoo fi pari ile ẹkọ giga fasiti.

Àkọlé fídíò, End SARS: Kemi jáde níle láti lọ bá mi ra oògùn ni mo gbọ́ pé ọlọ́pàá ti gbée- Ìyá Kemisol

Ṣaaju ni ikoko Kemisola ti ṣe orire nipa bi eeyan kan ṣe fún ni anfaani ẹkọ ọfẹ lati ile ẹkọ akọbẹrẹ titi de ile ẹkọ girama.

Anfaani yii n waye lẹyìn osu mẹsan ti awọn agbofinro gbe Kemisola ati awọn oluwọde mii, to kopa ninu iwọde Endsars losu kẹwa odun 2020.

Kemisola ati awọn ti wọn mu la gbọ pe wọn dana sun olu ile ẹgbẹ oṣelu APC ni Akure.

Ọgba ẹwọn Surulere ni ijọba ibilẹ iwo oorun Ondo lo wa, tó sí bimọ si lọjọ kẹrindinlogun osu kẹfa.

Okiki Kemisola kan, t'awọn ọmọ Nàìjíríà sí gbarata pe ko dara bo ṣe bimọ si ẹwọn.

Àkọlé fídíò, Olowo: Bí ìjọba bá ṣe àtúntò tún yẹ, Sunday Igboho yóò fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú wọn

Ọrọ Kemisola dayọ ni ọjọ kejilelogun oṣù Kẹfà nigba ti adajọ ile ẹjọ giga gba beeli rẹ.

Ikomọjade fun ọmọ Kemisola waye lẹhin to gba itusilẹ ni ọjọ Kẹtalelogun oṣù Kẹfà ni Akure.