Ọwọ́ NDLEA tẹ akẹ́kọ̀ọ́ fásitì tó n ta 'cookies' tí wọ́n fi oògùn olóro ṣe fún àwọn ọmọ́de

Oríṣun àwòrán, Ndlea nigeria
Ajọ to n gbogun ti lilo egboogi oloro ni Naijiria, NDLEA ti mu ọmọbinrin kan ati ọrẹkunrin rẹ, fun pe wọn n ta bisikiti ti wọn fi egboogi oloro ṣe fun awọn ọmọde nilu Abuja.
Ninu atẹjade ti ajọ NDLEA fi sita loju opo Twitter rẹ lo ti sọ pe ọwọ tẹ Rhoda Agboje.
Rhoda jẹ akẹkọọ fasiti, ati ọrẹkunrin rẹ, Ifeanyi Nwankwo, pe wọn n fi egboogi oloro pelo bisikiiti ti wọn n ta fun awọn ọmọ ileewe ati awọn eeyan mi laarin ilu, ti ko mọ iru iṣẹ ti wọn n ṣe.
Gẹgẹ bi ajọ naa ṣe sọ, aṣiri ikọ naa tu u, lẹyin ti ọwọ tẹ Rhoda t'ohun ti bisikiti naa mẹrin lọwọ rẹ lọjọ Aiku, ọjọ kejidinlogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2021.
Agbegbe NNPC Cooperative Estate ni Gaduwa, nilu Abuja, ni ọwọ ti tẹ ẹ lẹyin ti awọn kan fi ẹjọ rẹ sun pe o fun ọmọde kan ni bisikiiti naa jẹ.
- Wo àwọn ìwà to le è ṣe àfarawé lára ọ̀rẹ́, èyí tó le ṣekú pa ọ́
- Ta ni Mohammad Buba Marwa tó ṣẹ̀ṣẹ̀ di ọ̀gá àgbà àjọ NDLEA?
- Baba Suwe bọ́ lọ́wọ́ àìsàn, ó bẹ̀rẹ̀ tíátà padà
- Ọwọ́ agbófinró tẹ obìnrin tó gbé 'cocaine' sínú ojú ara rẹ̀ l'Abuja
- Ó ṣeésẹ kí ọkùnrin tó n mu àmujù ọtí ó maa lo ìwà ipá pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀
Iroyin sọ pe ọmọdebinrin naa bẹrẹ si ni ṣe were-were, ko le sun, bẹẹ lo n sọrọ bi ẹni to ni aarun ọpọlọ nitori oró bisikiiti naa lara rẹ.
Lasiko ti awọn oṣiṣẹ ajọ NDLEA n fi ọrọ wa Rhoda l'ẹnu wo lo jẹwọ pe oun ati ọrẹ rẹ kan ni wọn jọ n ṣe bisikiiti naa.

Oríṣun àwòrán, Ndlea nigeria
Ẹgbẹrun kan aabọ Naira si ni wọn ma n ta ẹyọ mẹta rẹ.
Iwadii ti wọn ṣe si ile ọrẹkunrin rẹ lo mu ki wọn o ri igba bisikiiti naa ti wọn fi egboogi oloro ṣe.
Bakan naa ni wọn ba awọn irinṣẹ ti wọn fi n ṣe e.
Afurasi naa sọ pe oun ma n ta a ni ibi ariya, fun awọn araalu ti ko mọ nkan ti wọn fi ṣe e, to fi mọ awọn ọmọ ileewe.
Bakan naa lo ma n gbe fun awọn ile itaja ati ile ijo gẹgẹ bi alagbata rẹ.
- "Iṣẹ́ fọga ni mo fi kọ́ ilé ńlá méjì, ti mo sì fi rán àwọn ọmọ mi lọ fásitì"
- Ṣé o fẹ́ lọ sí ọ̀run rere? Wo bí Naira Marley ṣe le ràn ọ́ lọ́wọ́ láti wọlé
- Ọkọ̀ agbépò gbiná ní Benue, ẹni mẹ́sàn án kú, ṣọ́ọ̀bù 72 ọlọ́já iyebíye jóná
- A ti ṣetán láti fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún òmìnira ilẹ̀ Yoruba, a ò níbi kankan ti a fẹ́ sálọ - Ọba Adetokunbo Tejuosoho
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Katsina bẹ̀rẹ̀ sí ń fi ajá ṣọ́ àwọn ilé ẹ̀kọ́ láti kojú àwọn ajínigbé















