Yeye Olokun of Lagos Omolara Fasola Fanimokun: Ọkọ mi kìí bọ òkun, "Elder" ni ní ṣọ́ọ̀ṣì àmọ́ ìdí nìyí tó fi bọ̀wọ̀ fún ìpè mi
"Ipe mi ni Oloriṣa olokun, iṣẹ ti mo si yan laayo ni iṣẹ Amofin lorilẹede Naijiria".
"Lati kekere ni mo ti maa n ri ara mi ti mo maa n wẹ, ṣere ninu omi"

Wolii ni Yeye Olokun tẹlẹ fun ogun ọdun ni ṣọọṣi. Ọmọ Eko ni baba rẹ amọ ọmọ ipinlẹ Edo ni iya rẹ.
Yeye Omolara Fashola to tun jẹ amofin nipa ọrọ oju omi ṣalaye bo ṣe yan lati di yeye Olokun leti okun eyi ti ọpọlọpọ maa n pe ni Yemoja nilẹ Yoruba.
- Ṣé o mọ iye òṣèré fíìmù Yorùba àti olórin tó bá ọdún 2020 lọ?
- Àwọn àmi méje tó ń tọ́ka sí pé oò kí ń mu omi bí ó ti tó
- 'Mo máa tó dìde lórí àìsàn', Muyiwa Ademola sọ̀rọ̀ látorí àkéte àìsàn rẹ̀
- 'Kí n máa lọ́ ayẹyẹ kiri 'torí ijó láì ṣe pé wọ́n pe mí ló sọ mí di DJ Kulet olórin Fuji nìkan'
- Ohun tí a mọ̀ nìyí nípa #IGotSurvivalFund owó ìrànwọ̀
- Àwọn ìgbésẹ̀ tóo lè fi so NIN rẹ̀ pọ mọ́ síìmù MTN, Glo, Airtel ati 9Mobile rẹ
- Nínú kó o fi omi fọ ìdi tàbí lo tííṣù fi fá a, Èwo ló rọrùn?
- Ṣé òótọ́ ni àwọn ará Amẹ́ríkà máa ń hán an lọ́wọ́ kan tí wọ́n bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀?

Ohun to yan laayo bayii dabii pe aṣa diran ni tori gẹgẹ bi Yeye ṣe sọ fun BBC Yoruba, ati ile baba ati ile iya rẹ ni wọn.

Lasiko ọkan lara ijọsin rẹ leti okun, o ba BBC Yoruba sọrọ lorii bi o ṣe jẹ ọmọ Musulumi to tun lo ogun ọdun ni ṣọọṣi gẹgẹ bii Kristẹni ati Wolii ijọ kan ko to wa gba ibi to ni ori da a lọ eyi tii ṣe bibọ okun.
Bakan naa o ṣalaye awọn nkan to gbagbọ ninu rẹ nipa aṣa ati iṣẹṣe Yoruba fun idagbasoke orilẹede pẹlu igbelẹyin imọ ofin.

Produced by Yemisi Oyedepo, Funmi Jokotade & Damilola Oduolowu



