EndSARS, Daniel Chibuike Ikeaguchi: ọlọ́pàá yìbọn pa Sleek ní Port Harcourt niléẹjọ́ bá bú N50 mílíọ̀nù, owó gbà má bínú

Oríṣun àwòrán, SLEEK DC/FACEBOOK
Aadọta miliọnu naira ni Adajọ ni ki ileeṣẹ ọlọpaa o san fun ẹbi Sleek.
Ile ẹjọ giga ipinlẹ Rivers kan to fikalẹ silu PortHarcourt ti paṣẹ pe ki ileeṣẹ ọlọpaa, ọga ọlọpaa Naijiria, kọmiṣọnna ọlọpaa atawọn ọlọpaa meji miran o san owo gba maa binu naa.
Awọn ikọ yii ni yoo san aadọta miliọnu naira fun ẹbi oloogbe Daniel Chibuike Ikeaguchi ti inagijẹ rẹ n jẹ 'Sleek'.
- Wo ohun tí Ọọ̀ni, Sultan Sokoto sọ nípa ọta ìbọn tó gbẹ̀mí Ọba Olúfọ́n
- Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ ASUU tí gbà láti fòpin sí ìyanṣẹ́lódí lẹ́yìn tí ìjọba gbà látí sàn N70bn ṣùgbọ́n...
- Látilẹ̀ ni mo ti fẹ́ràn orin ìjọ Kérúbù àmọ́ ẹlẹ́sìn mùsùlùmí àti krìstẹ́nì ni mí- Qdot
- Wo bí ilé ìwòsàn LUTH ṣe ń gba owó ibùsùn lọ́wọ́ àwọn aláìsàn, tí àwọn míràn sì ń sun ìta
Ni ọjọ kọkandinlogun, oṣu kẹsan an, ọdun 2020 lawọn ọlọpaa ikọ agbogun tiwa ijinigbe, Anti-Kidnapping Unit, ileeṣẹ ọlọpaa pa Sleek.
Ni ilu Port Harcourt ni ipinlẹ rivers to jẹ ẹkun guusuguusu Naijiria ni eleyii to mu ki wọn pe illeeṣẹ ọlọpaa lẹjọ itapa si ẹtọ ọmọniyan.
Ni ijoko ile ẹjọ naa meji lawọn ọlọpaa ko ti yọju ti wọn ko si tun ranṣẹ ki wọn to farahan ni ijoko ile ẹjọ naa to kẹyin lọjọ kẹtalelogun, oṣu kọkanla, ọdun 2020 lati wa pẹjọ tako ẹsun ti olupẹjọ naa n fi kan wọn.

Oríṣun àwòrán, SLEEK DC/FACEBOOK
Onidajọ S.C. Amadi ninu idajọ rẹ ni bi ọlọpaa ṣe ṣeku pa Sleek tako iwe ofin orilẹ-ede Naijiria ati pe bi wọn ko tun ṣe fi ọlọpaa to yin in nibọn pa naa jẹjọ ko bofin mu rara.
Amọṣa dipo biliọnu kan naira tawọn ẹbi Ikeaguchi n bere fun fun, aadọta miliọnu naira ni Adajọ Amadi naa paṣẹ ki wọn san fun ẹbi ologbe naa lẹyẹ o ṣọka.

Oríṣun àwòrán, SLEEK DC/FACEBOOK
Agbẹjọro fun ẹbi ologbe naa, Noble Njoku ṣe apejuwe idajọ naa gẹgẹ bi eyi to dara pupọ ti yoo si jẹ ifaleti fawọn ọlọpaa ti wọn n fi eeyan kọ ibọn yinyin.
Awọn obi Sleek, Dominic Ikeaguchi Oyekwu pẹlu ṣalaye pe idajọ naa yoo wo ọgbẹ wọn san de aaye kan bi o tilẹ jẹ pe ọmọ awọn ko le e pada saye mọ.
- Ọmọbìnrin tó tayọ nínú ìdànwó WAEC ọdún 2019 pẹ̀lú A1 méje ti kú
- Orúkọ Aisha Yesufu náà wọ inú BBC 100 Women tí a fi ń sọri àwọn obìnrin tó pegedé ní 2020
- Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
- Báyìí ni àgbàọ̀jẹ̀ agbábọ́ọ̀lù Diego Maradona ṣe wọ káà ilẹ̀ lọ lólú ìlú Argentina

















