Bank robbery: Àwọn ọlọ́pàá ti bẹ́ síta láti ṣàwárí àwọn olè 30 tó jówó kó ní Union Bank l'Ondo

Oríṣun àwòrán, Nigeria Police Force
Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Ondo ti sọ pe awọn akọṣẹ mọṣẹ ọlọpaa ti bẹ sita lati ṣe awari awọn adigunjale ti wọn yabo ile ifowopamọ Union Bank to wa niluu Ode-Irele nipinlẹ Ondo.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa l'Ondo, Tee Leo-Ikoro to fidi ọrọ naa mulẹ ṣalaye pe adigunjale naa to ọgbọn niye.
Ni deedee ago mẹrin irọlẹ ni awọn adigunjale naa rọna wọle si ile ifowopamọ Union Bank naa.
- Àwọn afurasí ajínigbé pa Olufon ti Ifon nípìnlẹ̀ Ondo, Oba Isreal Adewusi
- Ìgbín, iṣu, epo, àádùn, obì, iyọ àti oyin wa lára ohun ti a fi sọ ọmọ Ọọni lórúkọ!
- Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
- Ìtàn kíkùn lórí Mọ́ṣáláṣí Anabi ní Medina tó bẹ̀rẹ̀ lọ́dún 1440 sẹyin
- Ọlọ́pàá fìyà jẹ mí lọ́dún 2014, mò wà lẹ́yìn àwọn ọ̀dọ́ lórí ìwọde EndSARS- Fayemi
Leo-Ikoro sọ pe agọ ọlọpaa to wa niluu naa lawọn ọdaran naa kọkọ kọlu ki wọn to morile ile ifowopamọ nibi ti wọn ti ji obiti biti owo lọ.
Bakan naa, agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa fidi rẹ mulẹ pe awọn adigunle jale naa ji ọpọ ibọn ko lọ ni agọ ọlọpaa.
O ni ado oloro lawọn ọdaran ọhun lo lati fọ ibi tawọn ọlọpaa n ko ibọn pamọ si.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Amọ, Leo-Ikoro sọ pe ko si ẹni to ba iṣẹlẹ ọhun bo tilẹ jẹ wọn yinbọn fun awọn eeyan kan.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ko ṣai fidi rẹ mulẹ pe awọn adigunjale naa ko ni lọ lai foju wina ofin.
- Àpò òfìfo ni a bá nígbà tí a gbàjọba lọ́dún 2015, ṣùgbọ́n a ti ṣiṣẹ́ ribiribi - Ìjọba àpapọ̀
- Ìgbín, iṣu, epo, àádùn, obì, iyọ àti oyin wa lára ohun ti a fi sọ ọmọ tuntun Ọọni Ifẹ lórúkọ!
- Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀
- Nigeria police brutality probe: Ohun tí akọròyìn BBC rí rèé lásìkò ikọlù níbi ìwọ́de Lekki
- Àjọ Hisbah tó jẹ́ ọlọ́pàá Sharia ní Kano kọ lẹ́tà ìkìlọ̀ lórí lílo èdè 'Black Friday'













