Community Policing: Onímọ̀ ètò ààbò ní kìí ṣe ojúṣe ọ̀gá ólọ́pàá láti dá ọlọ́pàá agbègbè sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, @NTANewsNow
Ọlọpaa agbegbe, ti ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria n gbero lati dasilẹ ko le kẹsẹjari, laijẹ wi pe ijọba ṣetan lati maa fawọn ti wọn fẹ gba ṣiṣẹ lowo.
Onimọ nipa ọrọ eto aabo, Ọgbẹni Richard Amuwa to ba BBC Yoruba sọrọ, lo woye bẹẹ.
Ọgbẹni Amuwa sọ pe awọn ara ilu to ba fẹ ṣiṣẹ ọlọpaa agbegbe, nilo lati gba owo oṣu, bi bẹẹ kọ, wọn ko ni ṣiṣẹ naa tọkantọkan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Máṣe tijú láti gé ọmú rẹ to bá ṣàkíyèsí kóró nínú ọyàn, ilèra ló ṣe kókó - Ẹni tó ye àìsàn jẹjẹrẹ ọyàn
- Mímu ọtí líle àti oúnjẹ oní sítáṣì le è fa àrùn jẹjẹrẹ ọyàn - Onímọ̀
- Arap Moi, ààrẹ Kenya tẹ́lẹ̀ jáde láyé
- Àwọn òṣìṣẹ́ ọba ní Kwara sọ ara wọn sínú ààwẹ̀ àti àdúrà torí owó oṣù tuntun
- Ìtàn ìgbé ayé Arap Moi, ààrẹ kejì ní Kenya tí ọ̀pọ̀ ń rántí ìjọba rẹ̀ fún ìwà àjẹbánu
- Ìdùnnú ṣubú layọ̀ fáwọn obìnrin, ife ìtọ̀ tó ń dènà àrùn nílé ìgbọ̀nsẹ̀ ti dé
Onimọ nipa ọrọ eto aabo tun sọ pe, kii ṣe ojuṣe ọga ọlọpaa lati ṣe eto gbigba ọlọpaa agbegbe.
O ni awọn awọn alaṣẹ ipinlẹ kọọkan lo yẹ ki wọn wa awọn eeyan lawujọ lati ṣiṣẹ ọlọpaa agbegbe, nitori awọn lo mọ awọn eeyan wọn.
Ọga agba ọlọpaa Mohammed Adamu lo paṣẹ fawọn ọga ọlọpaa ipinlẹ kọọkan lati forikori pẹlu awọn ọba alaye atawọn olori awujọ k'eto naa kẹsẹjari.

Ṣugbọn Ọgbẹnu Amuwa ni ọga agba ọlọpaa ko ni ohun kan ṣe pẹlu ọlọpaa agbegbe nitori ko si lọwọ ijọba apapọ.
O fi Gomina ipinlẹ Imo tẹlẹ, Rochas Okorocha ṣe apejuwe ijọba ipinlẹ to ti ṣe agbekalẹ ọlọpaa agbegbe ri.
Ọgbẹni Amuwa ni Rochas forikori pẹlu awọn ọba alaye atawọn olori awujọ lati gba awọn eeyan ṣiṣẹ, bakan ni ijọba rẹ si n fun wọn lowo.
O ni ijọba apapọ ati ọga agba ọlọpaa ni Naijiria ko mọ itumọ ọlọpaa agbegbe.
Onimọ nipa ọrọ eto aabo, Ọgbẹni Amuwa ni ko lee si eto aabo to mọyan lori ti ijọba ba kọ lati sanwo fawọn ti wọn fẹ gba gẹgẹ ọlọpaa agbegbe.













