Illegal Orphanage: Ìjọba ti ayédèrú ilé ọmọ aláìlóbìí pa, ọmọdé mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n gbòmìnira

Ile ọmọ alailobi

Awọn alaṣẹ tọrọ kan lorilẹede Naijiria ti ko agadagodo silẹkun ile ọmọ alailobi kan ti ko niwe ofin ni ipinlẹ Kaduna, ti wọn si tu ọmọde mẹtadinlọgbọn silẹ.

Ọjọ ori awọn ọmọ naa wa laarin ọdun mẹta si mejila.

Agbẹnusọ ile iṣẹ Ọlọpaa ipinlẹ Kano, DSP Abdullahi Haruna sọ fun BBC pe, o to ọmọde mọkandinlogun tawọn tu silẹ nile awọn ọmọ alailobi Du Merci niluu Kano.

Bakan naa ni Abdullahi sọ pe, ile iṣẹ ọlọpaa tun tu awọn mẹjọ miiran silẹ nile awọn ọmọ alailobi Du Merci to wa niluu Kaduna.

Ile iṣẹ ọlọpaa sọ pe, eleyi ṣeeṣe pẹlu iranlọwọ ajọ NAPTIP to n gbogun ti fifi eeyan ṣe owo ẹru lorilẹede Naijiria.

Agbẹnusọ fun ile iṣẹ ọlọpaa ni, ayederu ile ọmọ alailobi nibi tawọn ti tu awọn ọmọde naa silẹ.

Ile ọmọ alailobi

Oludamọran fun Gomina ipinlẹ Kano, Fatima Abdullahi Dala, to ba BBC sọrọ ṣalaye pe Du Merci ti wa fun bi ọdun mẹẹdọgbọn lai niwe ofin.

O wa rọ awọn eeyan Kano lati fi to ijọba leti, ti wọn ba ṣakiyesi iru ile ọmọ alailobi bẹẹ lagbegbe wọn.