Coronavirus Ghana: Ààrẹ Nana Akufo-Addo ti wọ́lé ìyàsọ́tọ̀ ọlọ́jọ́ mẹ́rìnlá

Oríṣun àwòrán, Facebook/Nana Akufo-Addo
Aarẹ orilẹede Ghana yoo wa ni yara iyarasọtọ fun ọjọ mẹrinla lẹyin ti iwadii fihan pe o ti ni ipade pẹlu ẹni to ni arun Coronavirus.
Ninu atẹjade ti Minisita fun eto iroyin, Kojo Oppong Nkrumah fi lede ni wọn ti fi lede bẹẹ.
Nkrumah ni awọn dokita ti gba Aarẹ ilẹ Ghana, Nana Akufo ni imọran lati wa ni iyasọtọ fun ọjọ mẹrinla bẹrẹ lati Ọjọ Kẹrin, Oṣu Keje, ọdun 2020.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
O fikun pe aarẹ naa gba lati tẹle amọran awọn dokita naa nitori o kere tan eniyan kan ninu awọn ti wọn jọ n ṣiṣẹ pọ ti ko arun Coronavirus.
Ijọba ni ayẹwo fihan bayii pe, aarẹ naa ko ni arun Coronavirus, amọ o pọn dandan lati wa ni iyasọtọ ni asiko yii.
Ijọba ilẹ Ghana fikun pe, Nana Akufo yoo ma a ṣiṣẹ lọ gẹgẹ bi aarẹ ni igba ti o ba fi wa ni iyasọtọ.
- Ọ̀pọ̀ èèyàn tí kò yin Ajimobi lojú ayé, tó ń yìn-ín lẹ́yìn ikú, yóò jẹ ìyà - Oníwáàsí
- Ọ̀pọ̀ ìgbà ní Hushpuppi àtàwọn èèkàn PDP ti ya fọ́tò ní Dubai, EFCC ẹ wádìí wọn - APC ń lọgun
- Àwòrán rèé nípa àwọn gbajúmọ̀ tó ti bá Hushpuppi ṣe
- Mo ti bá ọmọ ọwọ́ mẹ́ta lòpọ̀ sẹ́yìn, ọmọ oṣù mẹ́ta ló ṣìkẹrin - Afurasí jẹ́wọ́
Oluwọde tako ele owo epo ni Ghana

Ẹkunwo epo bẹntiroolu to waye ni orilẹede Ghana laipẹ yii ti nfa ẹhonu bayii, tawọn oluwọde si ti fun ijọba orilẹede Ghana ni gbedeke ọsẹ meji lati fi mu ayipada ba ọwọngogo owo epo bẹntiroolu to waye lorilẹede naa.
Awọn oluwọde ọhun ti wọn ko si inu asọ pupa ati dudu, rin kaakiri awọn opopona to lorukọ nilu Accra, tii se olu ilu oruilẹede Ghana.

Lara awọn ohun ti wọn kọ si ara patako ti wọn gbe dani ni awọn ọrọ bii, 'Aarẹ tẹti si awọn awakọ', " Kii se ileri too se fun wa niyi', ati 'Aarẹ, ẹ din owo yi ku.'
Ohun ti wọn n pariwo ninu iwọde wọn ni wipe, bi owo epo se n gbe ẹnu lọ soke ni igbe aye n nira fun araalu nibẹ.
Kini iwadi BBC sọ?
Ninu ọrọ to ba Akọroyin BBC, Thomas Naadi sọ, oludari ajọ to n risi katakara epo lorilẹede Ghana, ọgbẹni Duncan Amoah ni wahala wa lori eto okoowo ọrọ epo.
"Owo osu lorilẹede yii ko le fi aaye silẹ fun ẹkunwo kankan lori epo. Ohun ta n beere ni pe ki ijọba o o yẹ owo ori ti wọn n fi si ori epo wo. Ni orilẹede Ghana loni, owo ori lita epo kan le ni dọla kan owo orilẹede Amẹrika lọ. Ti ọrọ ba si ti n di ti pe owo to kere ju ti osisẹ n gba ko ba lee ra lita epo kan, wahala wa niyen o."

Oríṣun àwòrán, AFP/Getty Images
Awọn oluwọde naa wa n ke si ijọba lati din iye akanse owo ori to n fi si ori epo bẹntiroolu ku ni ida mẹẹdogun ninu ọgọrun.
Amọsa, ileesẹ epo rọbi orilẹede Ghana ti sọ wipe ohun ko lagbara lati sọ iye ti owo epo bẹntiroolu yoo ba de atipe gbogbo igbesẹ to yẹ ni gbigbe ni wọn ti gbe lati rii pọ ipa ẹkunwo naa dinku lara araalu.
Ireti wa wipe Aarẹ Akufo Addo yoo fesi si ọrọ ọhun lasiko ti yoo ba gbogbo awọn ọmọ orilẹede naa sọrọ ni ọjọọbọ.













