Rotimi Akeredolu: Oluwarotimi Akeredolu di gómìnà fún ìgbà kejì ní ìpínlẹ̀

Oríṣun àwòrán, @GboyegaOyetola
Gomina ipinlẹ Ondo, Oluwarotimi Akeredolu ti ṣe ibura lati sin ipinlẹ Ondo ati orilẹede Naijiria.
Gomina Akeredolu ṣe ibura naa lasiko ti wọn burawọle fun un gẹgẹ bi gomina ipinlẹ Ondo ni saa keji.
Lucky Aiyedatiwa to dije dupo gẹgẹ bi igbakeji Akeredolu naa ni wọn ti bura wọle fun ni igba akọkọ gẹgẹ bi igbakeji gomina.
- Ìrọ́ ní ò, a o fí ìgbà kankan fí Olupelumi Fagboyegun, Ìbátan Akeredolu sí ẹ̀wọ̀n- Iléẹ́jọ́ ìpínlẹ̀ Ondo
- Seyi Makinde, Akeredolu, òfo ni kùrù-kẹrẹ yín lọ́dọ̀ Buhari lórí ìpèsè ààbò - Falana
- Gbogbo ẹ̀yin Fulani darandaran tó wà ní ìgbó ìjọba ní Ondo, ọjọ méje lẹní láti pòórá - Gomina Akeredolu
- Kíni àwọn gómínà láti Àríwá Naijiria sọ lórí ìjà ẹlẹ́yàmẹ̀yà ní Shasha?
Aiyedatiwa to wa lati iha guusu ipinlẹ Ondo, wa si ini iburawole naa pẹlu omo ati iyawo rẹ.
Aiyedatiwa ti fi igba kan jẹ kọmisonna fun Ajọ Niger Delta Commission ni ipinlẹ Ondo, ko to di igbakeji Gomina.
Iyawo gomina Akeredolu, Betty Anyanwu, ọmọ ati ọmọọmọ gomina naa lo wa si ibi iburawọle naa.
Awọn gomina to fi mọ ọkan lara awọn adari ni ẹgbẹ oṣelu APC, Asiwaju Bola Ahmed Tinubu wa nibi iburawọle to waye ni gbagede Dome, ni ilu Akure, nipinlẹ Ondo.
Saaju ni gomina ipinlẹ Ondo, Oluwarotimi Akeredolu ti kede isinmi fun awọn oṣiṣẹ loni ọjọ iburawọle rẹ ni ipinlẹ naa.
Ọpọlọpọ iṣoro lo n koju ipinle naa, to fi mọ eto aabo to dẹnukọle, ijinigbe ati ija laarin awọn agbẹ ati darandaran to ti mu ọpọ ẹmi ṣofo nipinlẹ naa.
















