Olusegun Obasanjo: Ibrahim Ibuoye, ẹni ọgọ́ta ọdún dèrò ilé ẹjọ́ nítorí ó wọ inú oko Obasanjo láì gba àṣẹ

Oríṣun àwòrán, Others
Ẹni ọgọta ọdun Ibrahim Ibuoye to foju bale ẹjọ majisireeti kan ni ipinlẹ Ogun nitori o wọ oko aarẹ orile-ede Naijiria nigba kan ri Olusegun Obasanjo ni Ota lai gba aṣẹ.
Ẹsun mẹrin ni wọn fi kan Ibuoye lbrahim, o da omi alaafia agbegbe naa ru, o fi tipa wọ ori ilẹ onilẹ, o ba n kan jẹ, o si tun gbimọ ọtẹ, eyi to si ti ni oun ko jẹbi ikankan ninu awọn ẹsun naa.
Insipẹkitọ ọlọpaa to wa nidi ọrọ naa, Rosemary Samson sọ fun ile ẹjọ pe ẹni a fẹsun kan yii ati awọn miran to ti salọ lo jọ ṣe ẹsẹ naa ni ọjọ kẹrindinlọgbọn, oṣu kẹjọ, ọdun 2020 ni Obasanjo Farm Ltd Ota.
Samson ni ọkunrin ohun ati awọn ẹmẹwa rẹ mu nkan ija lọwọ, ti wọn si fi agidi wọ inu oko naa ti o si da ipaya silẹ laarin awọn eniyan, eyi tumọ si pe wọn da omi alaafia ibẹ ru.
Bakan naa ni o ni ọkunrin ohun ba mọto Hinda Accord pelu ami idanimọ LSD 655 EV, to jẹ ti Kazeem Ajiboye jẹ pẹlu.
- Kí ló mú Obasanjo ti ilẹ̀kùn mọ́ ẹbí, òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ ní ibi òkú àna rẹ̀?
- Mi ò fẹ́ ìrànwọ́ ẹgbẹ́ òṣèré, àwọn kọ́ ló kóbá mi- Chief Kanran
- Wo ọ̀nà tí o le è gbà láti má san àfikún owó iná ẹ̀lẹ́ńtíríìkì tuntun
- Mi o tíì rí olórí tó fẹ́ràn Naijiria tó Baba Obasanjo- Yoruba Council of Elders
- Buruji Kashamu jẹ́ ènìyàn tó nífẹ̀ aráàlú- Gómínà Dapo Abiodun
Ọlọpaa naa fi kun un pe eyi tako ofin Criminal Code ipinlẹ Ogun, ọdun 2006
Adajọ Majisirati oun B. S Abdulsalm gba pe ki wọn gba oniduro fun ọkun rin naa pẹlu ẹgbrun lọna ẹẹdẹgbẹta naira gẹgẹ bi owo itanran, pẹlu oniduro meji.
Abdulsalam fi kun un pe, awon oniduro rẹ gbodọ jẹ olugbe adugbo ile ẹjọ ki o si ni iṣẹ gidi lọwọ pẹlu ẹri iwe owo oei to n san deede fun ijọba ipinlẹ Ogun.
Ile ẹjọ tun pa a lașẹ pe oniduro naa gbọdọ ni ilẹ ni ayika ibi ti ile ẹjọ Majisisreeti ohun wa pẹlu ki wọn to le gba oniduro fun.
Wọn ti sun igbẹjọ si ọjọ kẹrinla oṣu yii.
- Bí ìjà bá wà láàrin èmi àti Olubadan, a ó yanjú ẹ ní pẹ̀lẹ́kùtù, ọ̀rọ̀ bàbálọ́jà kò lè dìjà
- Àwọn ará ìlú Ikarẹ Akoko ń ṣọ̀fọ̀ Ọba Adegbite, Ọwá Ale Ikarẹ tó wàjà
- Ọba Saudi Arabia yọ ọmọ rẹ̀ àti àbúrò rẹ̀ kúrò nípò nítorí ìwà àjẹbánu lórí owó tó yẹ fún ààbò ìlú
- Ìjàmbá ọkọ̀ tó ṣẹlẹ̀ sí Adams Oshiomole kìí ṣe ojú lásan, àwọn kan ló fẹ́ pa á- APC
- Sinimá àwòdamiẹnu, Ẹ̀fáńjẹ́líìsì jìyà àjẹmumi nílé aṣẹ́wó l'Ejigbo ní ìlú Eko
- Iléeṣẹ́ ìròyìn Daily Trust gbọdọ̀ san N6 bilion nítorí ìbanilórúkọjẹ́- Femi Fani Kayode
















