Oyo: Ṣeyi Makinde yan ọmọ Hausa gẹ́gẹ́ bíi olùrànlọ́wọ́ pàtàkì

Oríṣun àwòrán, @others
Gomina Seyi Makinde yan Dokita Olufunmilayọ Salami ati Alhaji Ahmed Murtala pẹlu awọn miran gẹgẹ bi oludamọran tuntun.
Ta ni Dokita Olufunmilayọ Salami ti Makinde yan?
Iṣẹ ikọṣe iṣegun itọju awọn ọmọde ni onimọ iṣegun Olufunmilayọ Salami kọ jade ni fasiti Benin.
O n ṣiṣẹ itọju ọmọde ni Atlanta ni Georgia ni orilẹ-ede America.
O din diẹ logun ọdun lo ti n ṣiṣẹ iṣegun to ti n tọju ọmọde.
Funmilayo ti gba ọpọlọpọ ami ẹyẹ to fihan pe o dantọ lẹnu iṣẹ to yan laayo lati maa tọju awọn ọmọde.
Ta ni Alhaji Ahmed Murtala?
A bi Ahmed Murtala ji ijọba ibilẹ Nasarawa to wa ni ipinlẹ Kano ni ariwa Naijiria.
O lọ sile iwe St Brigid Boys ni Mokola nilu Ibadan fun ẹkọ alakọbẹrẹ ati ti Community Grammar School ni Mọkọla fun girama.
Ahmed ni Gomina Makinde ni ko maa ṣiṣẹ bii alagata laarin ijọba ipinlẹ Oyo ati awọn Hausa / Fulani ti wọn fi ipinlẹ Oyo ṣe ibujoko wọn.
Oun naa ni yoo maa ṣoju gbogbo ọmọ ilẹ Hausa to fọnka kaakiri ipinlẹ Ọyọ paapaa julọ lori ọrọ ija awọn agbẹ ati awọn darandaran.
Ṣeyi Makinde yan ọmọ Hausa gẹ́gẹ́ bíi olùrànlọ́wọ́ pàtàkì
Dokita Olufunmilayọ Salami lo fun ni olubadamọran pataki lori eto ilera nigba ti o fun Alhaji Ahmed Murtala ni olubadamoran pataki lori ọrọ awọn agbegbe ti hausa pọ si.

Oríṣun àwòrán, @others
Alhaji Ahmed yii ni o jẹ olubadamọran kinni fun gomina Seyi Makinde lori ọrọ awọn Arewa to jẹ iran Hausa ni ipinlẹ Oyo.
- 'Kò ní sí ìdíwó mó nínú ìṣàmúló ètò ìṣúná ìpínlẹ́ Oyo'
- Èrò àwọn ọmọ Naijiria yàtọ̀ lórí ohun ìní Seyi Makinde
- Olúbàdàn, ẹ bá wa bẹ́ Seyi Makinde kó tú wa sílẹ̀ - Oyo NURTW
- Àwọran bí àwọn òṣìṣẹ́ Ìpínlẹ̀ Oyo ṣe f'aṣọ ìbílẹ̀ rántí àyájọ́ ọjọ́ àṣà
- Makinde vs Adelabu: Ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ ní Nàìjíríà ní yóò yanjú ọ́rọ́ ìdìbò Gómìnà Oyo
Bakan naa lo yan Oloye Jacob Adetoro gẹgẹ bii alaga ẹka ti yoo maa mojuto Federal Constituency Liason Officers.
Seyi Makinde tun darukọ awọn aṣoju mẹrinla ti yoo maa ṣoju ẹkun kọọkan ni ipinlẹ Oyo nile ijọba apapọ.
Arabinrin Olubamiwo Adeosun to jẹ akọwe agba ipinlẹ Oyo lo buwọlu lẹta awọn ti Makinde ṣẹṣẹ yan sipo naa.
Ninu atẹjade ti olubadamọran fun Seyi Makinde lori iroyin iwe iroyin, Moses Alao fi sita lo ti fidi ikede yii mulẹ.
Awọn mẹrinla to yan ni Alhaji Ajibike Osuolale Lateef (Iseyin, Itesiwaju, Kajola and Iwajowa); Alhaji Salami Lukman Adisa (Saki East, Saki West and Atisbo); Alhaji Afees Tijani (Orelope, Irepo and Olorunsogo).
Hon. Ganiyu Laaro (Oriire, Ogbomoso North and Ogbomoso South); Mr. Sanjo Akintola (Ogo-Oluwa and Surulere); Mr. Wale Ogunmola (Afijio, Oyo West, Oyo East and Atiba); Hon. Monsuru Oduola (Ibarapa North and Ibarapa Central) naa tun wa nibẹ.
Gomina Makinde tun yam Honọrebu Femi Josiah gẹgẹ bii olubadamọran keji ti yoo maa mojuto ọrọ awọn agbegbe to ku yatọ si ti Hausa ti Alhaji Ahmed.
Saaju ni Gomina Makinde ti kọkọ ṣeleri fun awọn ọdọ ipinlẹ Niger fun un ni ami ẹyẹ gomina to dantọ julọ loṣu kẹfa to gori aleefa.
Makinde ni oun yoo yan agbenusọ kan ti yoo ma ri si ọrọ awọn iran Hausa ati fulani to fi ipinlẹ Oyo ṣe ibugbe nigba naa.
- Àjọ tó n rí si ọ̀rọ̀ fásitì (NUC) kéde ayédèrú Ọjọ̀gbọ́n tó tó ọgọ́rùn ún
- A ó kàn sí mọ̀lẹ́bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n tó kú létí ná kí a tó kéde orúkọ wọn-Iléeṣẹ́ Ọgbà ẹ̀wọ̀n
- Òṣìṣẹ́fẹ̀yìntì, ọmọ ọdún 71 wọ gbaga ọlọ́pàá fún pípe iléeṣẹ́ kan fún ìgbà 24, 000
- Bàbá mi fún mi ní kíndìnrín rẹ̀ láti dóòlà ẹ̀mí mi- Sam
















