Sallah: Ẹyin ará Ondo, Eko, Ogun, Osun, Ọyo, ẹ gbàdúrà ò!

Àwọn gómìnà Ìwọ̀-Òòrùn

Oríṣun àwòrán, Google

Àkọlé àwòrán, Àwọn gómìnà ní ẹkùn Ìwọ̀-oorun Naijiria ti késí àwọn ọmọ Naijiria lati lo asiko ọdún yìí láti fi gbàdúrà fún orílẹ̀èdè Naijiria.

Gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu ti kesi awọn ọmọ Naijiria lati lo asiko ọdun salah yii lati fi gbadura fun alaafia lorilẹede Naijiria.

Akeredolu ninu atẹjade to fi lede sọ wi pe adura nikan lo le sẹgun eto aabo to mẹhẹ lorilẹede Naijiria, eleyii ti o ti jasi iku awọn ẹlomiran ni awujọ.

Ninu ọrọ tirẹ, Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ni ki awọn ọmọ Naijiria lo asiko yii lati fi wa ilọsiwaju orilẹede Naijiria, ki wọn si sọra fun ọrọ agan to le fa iyapa ati ẹlẹyamẹya lorilẹede Naijiria.

Àkọlé fídíò, ''Ọjà ẹran àgbò kò yá bí ti ọdún tó lọ''

Bakan naa ni Gomina ipinlẹ Ogun, Dapo Abiodun, Gomina ipinlẹ Ọyo, Seyi Makinde naa pe fun ki awọn ọmọ Naijiria ati awọn ẹlẹsin musulumi lo asiko Sallah yii lati fi kọ ẹkọ pataki lara ojisẹ Allah, Ibrahim to ni ibẹru Ọlọrun, to si pa ofin rẹ mọ titi ọjọ aye rẹ ninu ifẹ.

Gomina ipinlẹ Ọyo ni tire wa rọ awọn ọmọ Naijiria lati gbe igbe aye mimọ, ifẹ, ododo, ibẹru Ọlorun ati ise ore, gẹgẹ bi awọn ohun amuyanga ti eniyan le ko ninu igbe aye Ojisẹ Ibrahim nigba aye rẹ.

Àkọlé fídíò, Oro Festival: Àwọn olórò ní ọdún Màgbó ló ń gba ibi lọ, kó ire wọlé ní Ikorodu