Soyinka: Ohun gbogbo ti dẹnu kọlẹ̀ la ṣe gbọdọ̀ gbé ìgbésẹ̀ pàjáwìrì

Oríṣun àwòrán, @Opetuyii
Yoruba ni agba ti ko ba kẹun sọrọ, yoo kẹ itan sare nitori agba kii wa lọja, ki ori ọmọ tuntun wọ.
Idi ree ti ilumọọka alami ẹyẹ agbaye, Ọjọgbọn Wọle Ṣoyinka fi n lọgun pe aarẹ orilẹede yii, Mohammadu Buhari pe yoo dara ko kede pe nnkan ko fararọ lawọn ipinlẹ to wa nilẹ Yoruba lẹka eto aabo, ti ohun gbogbo si ti dẹnu kọlẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọdún Orò ń sọ àwa obìnrin sí ìgbèkùn, ẹ̀wọ̀n, tó sì ń tẹ ẹ̀tọ́ wa lójú - Àwọn obìnrin Ikorodu faraya
- Èèyàn mẹ́rìnlá tí ọpọlọ wọ́n pé la buwọ́lù bíi kọmísọ́nà l‘Oyo - Olórí ilé aṣòfin kan sáárá
- Èmi àti Saheed kìí ṣe ọmọdé, a ti jọ ṣe Sinimá papọ̀, èyí túmọ̀ sí pé ìjà ti parí - Fathia Balogun
- "Mo fẹ́ pa ara mi torí ojú àbùkù tí wọn ń fi wò mí pé mo fi iṣẹ́ abẹ bímọ"
- Fulani kò leè dúró, táa bá lo ohun ta jogún lọ́dọ̀ àwọn bàbá wa - Sunday Igboho
Soyinka, ẹni to mu igbe yii bọnu lasiko to n bawọn akọroyin sọrọ nilu Akurẹ nibi ayẹyẹ kan, tun salaye pe o n bọ, o n bọ, awọn laa dẹ de, amọ laye ode oni, oju ni wọn n mu to, nitori eto aabo ti mẹhẹ nilẹ Kaarọ Oojire kọja sisọ, o si yẹ ko wa nkan se nipa rẹ.

Oríṣun àwòrán, @Opetuyii
"Oniruuru ọna ni eto aabo fi mẹhẹ, paapa nipinlẹ Ondo, to si tun jẹ ohun ibanujẹ nla yika orilẹede Naijiria, nitori naa, igi gogoro ma gun mi loju, ati okeere laa ti lọọ, idi si ree taa fi gbọdọ gbe igbesẹ pajawiri lati rẹyin aifararọ eto aabo naa."
- Ọjà Àgbáláta ní Badagry rèé, níbití ẹran ejò ti dùn ju ẹran adìẹ lọ
- Lórí ìmọ̀ràn Sunday Igboho, Ẹlẹbubọn ní yóò dára kí Yorùbá padà sí àmúlò èròjà ìbílẹ̀ fún ààbò
- A kò mọ̀ọ́mọ̀ pa ọlọ́pàá mẹ́ta, aráàlú kan, ó ṣèèsì ni, ajínigbé la pè wọ́n - Iléeṣẹ́ ológun
- Sowore àti àwọn ọmọ ẹgbẹ Revolution Now kò ṣẹ̀ ṣófin lórí ìwọ́de, ẹ tú wọn sílẹ̀ - NLC
- Òṣùká kékeré kò rẹrùn àgbà, orílẹ́èdè Nàìjíríà ṣòro púpọ̀ láti darí - Ibrahim Babangida
- Sowore ṣèpàdé pẹ̀lú Nnamdi Kanu láti dojú ìjọba Nàíjíríà bolẹ̀ - Àjọ DSS
Soyinka ni iwa isekupani ni aimọye ọna ti gba akoso ni gbogbo ọna lẹkun iwọ oorun guusu Naijiria, ti iwa ijinigbe naa ko si gbẹyin, wọn si ni ma fi oko mi sọna, ọjọ kan bayii ni eeyan maa n kọ ọ.








